Akure Baby on the Altar: Wọ́n fi orúkọ aya Akeredolu sọ ọmọ tuntun tí wọ́n bá ní pẹpẹ ṣọ́ọ́ṣì

Ọmọ ti wọn gbe ju si ori pẹpẹ ile ijọsin Kerubu ati Serafu Holy Trinity ni opopona Ọda n'ilu Akure n'ipinlẹ Ondo ti ẹnikẹni ko mọ awọn obi rẹ lo ti bẹrẹ igbe aye tuntun n'ile awọn ọmọ alailobi t'ijọba ipinlẹ Ondo.
Ọmọ naa to jẹ ọmọbirin ni wọn ti sọ ni Betty Emmanuella Akeredolu, lẹyin tawọn oṣiṣe ile iṣẹ ijọba ipinlẹ Ondo to n ri si ọrọ awọn obirin ati idagbasoke awujọ gba a s'ọdọ.
Adele akọwe agba ile isẹ naa, Arabirin Foluke Tunde-Daramola fi idaniloju han pe ọmọ naa ni yoo gba itọju to peye n'ile awọn ọmọ alailobi ti o wa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- "Màá pa màálù fún ọ, ọmọ mi Khadija, tí mo bá rí ọ gbà padà lọ́wọ́ ajínigbé"
- Ìrìn-àjò Baba Suwe pẹ̀lú àjọ NDLEA lórí bó ṣe ''yàgbẹ́ tì'' ní àtìmọ́lé
- Wo àwọn gbajúmọ̀ aláwàdà Yorùbá méje tó ti kú saájú Baba Suwe
- Wo ìdí tí àwọn Ọba aládé mẹ́rin yìí ṣe darí ìfẹ̀hónúhàn l'Ekiti
- Ilé ẹjọ́ kéde àwọn jàndùkú gẹ́gẹ́ bíi ẹgbẹ́ agbésùmọ̀mí
- Kí ló ń dá ọlọ́pàá dúró láti gbé Rahmon Adedoyin àti ọmọ rẹ̀ relé ẹjọ́ lórí ikú Timothy Adegoke?
O wa koro oju si bi awọn eeyan kan ṣe n gbe ọmọ sọnu lai ro ti irora oyun nini ati ti ọjọ ikunlẹ.
"Ọpọlọpọ ohun lo le ṣ'okunfa bi gbigbe ọmọ sọnu ṣe n peleke sii lawujọ.
"Itọju ọmọ ni kii ṣe ohun ti a le f'ọwọ yẹpẹrẹ mu, nitori naa ẹni ti ko ba tii ṣetan ni lati jina si ibalopọ tabi ki o daabo bo ara rẹ".
O ni bo tilẹ jẹ pe awọn oogun kan wa ninu ọra lẹgbẹ ọmọ naa lakoko ti wọn rii, ọmọ naa lo wa ni alaafia to si n ṣere rẹ lati igba to ti de ọdọ wọn.
Alukoro ileesẹ ọlọpa ni ipinlẹ Ondo, Funmi Odunlami sọ fun BBC Yoruba pe, awọn ti bẹrẹ iwadi lati ṣawari iya ọmọ naa.

Bawo ni wọn ṣe raaye gbe ọmọ naa sinu ṣọọṣi lasiko ti ilẹkun wa ni titi pa?

Igbe haa, hee, ta lo ni ọmọ, ikunlẹ abiyamọ o, lo gba ẹnu awọn olugbe ilu Akure kan ni aarọ Ọjọru, nigba ti wọn sadede ri ọmọ tuntun jojolo kan ninu ile ijọsin Kerubu ati Serafu Holy Fountain.
Agbegbe Oda road, nilu Akure, tii se Olu-ilu Ipinle Ondo ni isẹlẹ naa ti waye ni aarọ ọjọ isẹgun.
Ẹjẹ ọrun naa ni ko le ju ọmọ ọsẹ kan lọ, ti wọn si fi asọ alawọ eweko kan we, ki wọn to gbe si ori pẹpẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Bàbá mi máa ń sunkún torí bí kò ṣe le padà ṣeré tíátà mọ́ - Ọmọ Baba Suwe
- "Lẹ́yìn ti mo lo ọdún 42 lọ́gbà ẹ̀wọ̀n, wọ́n tú mi sílẹ̀ pé ń kò jẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn"
- Clem Ohameze, òṣèré tíátà ní àìlera, ó ń bẹ̀bẹ̀ àdúrà lórí iṣẹ́ abẹ
- N kò rán ẹnikẹ́ni láti pín ìrẹ̀sì àti ẹ̀wà tórí ìbò ààrẹ 2023 - Bola Tinubu figbe ta
- Kọmísánà ọlọ́pàá tú àṣírí bí ọmọ Rahmon Adedoyin ṣe ju òkú Timothy Adegoke sígbó, tó na pápá bora
- Wọ́n ní ajé wà lárá ọkọ mi ní wọ́n ṣe lò ó - Opó Timothy Adegoke gbarata
- Ẹ lọ san ₦20bn owó ìtanràn fún Sunday Igboho títí January - Iléejọ́ fọnmú fún DSS
- Ṣé lóòtọ́ ni àjọ EFCC mú Femi Fani-Kayode?
- Kò sí ìfẹ̀míṣòfò kankan ní Lekki Too Gate, àlọ́ àpamọ̀ lásán ni èsì ìgbìmọ̀ EndSARS - Lai Mohammed
- Awuyewuye súyọ lórí fídíò òkú Baba Suwe tó lu ayelujára pa
- Bí àyẹ̀wò òkú Timothy Adegoke, akẹ́kọ̀ọ́ fásitì OAU tó kú sílé ìtura, ṣe wáyé rèé
Oludasilẹ ijọ naa Biṣọbu John Ikoko, lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ lori bi isẹlẹ naa se waye ni oun ni oun ri ọmọ naa lẹyin toun gbọ igbe ọmọ tuntun latinu ile ijọsin, lẹyin adura owurọ ninu ile rẹ ti ko jinna si ile ijọsin naa.
Gẹgẹ bi ọrọ ikoko, kete ti ohun si ilẹkun ile ijọsin naa, ni oun ri ọmọ tuntun ni ori pẹpẹ (Altar), to n sunkun kikan kikan.
O salaye pe pẹlu bi ọrọ se ri, o han gbangban wipe iya ọmọ naa ni yoo gbe ọmọ naa sibẹ nitori o ko awọn eroja kan sẹgbẹ ọmọtuntun ọhun.
Awọn eroja naa si lo jẹ awọn nnkan eelo bii aṣọ, oogun oyinbo, ati ike-ifọmọlounjẹ taa mọ si feeding bottle.
Ojisẹ Ọlọrun naa fikun pe, iya ọmọ naa lo seese ko gba ferese ile ijọsin naa wọle bi o ti je wipe titi pa pẹlu kọkọrọ ni ilẹkun ile ijọsin naa wa.
O sọ siwaju pe, ohun ran iyawo oun lọ si agọ ọlọpa to wa ni Ala lati fi ọrọ naa to awọn agbofinro leti.
Lẹyin wakati kan si akoko naa, awọn ọlọpa lati agọ ọlọpa to wa ni Ala de si ile-ijọsin naa, wọn si ti gbe ọmọ tuntun naa lọ.





















