Banditry in Nigeria: Ilé ẹjọ́ kéde àwọn jàndùkú gẹ́gẹ́ bíi agbésùmọ̀mí

Oríṣun àwòrán, facebook/Offiong Enoh
Ile ejọ giga kan niluu Abuja ti kede awọn janduku gẹgẹ bii ẹgbẹ agbesunmọmi.
Nigba to n ṣedajọ lori ọrọ naa, adajọ Taiwo Taiwo sọ pe awọn iwa ati iṣesi awọn ẹgbẹ janduku ti orukọ wọn n jẹ Yan Bindiga ati Yan Ta'adda jẹ ti igbesumọmi.
Idajọ yii lo waye lẹyin ẹjọ ti ijọba apapọ pe lati ipasẹ ileeṣẹ to n ri si eto idajọ.
- Wo àwọn gbajúmọ̀ aláwàdà Yorùbá méje tó ti kú saájú Baba Suwe
- Bí DSS, DIA ṣe mú Igboho ati Kanu fihàn pé wọn kájúẹ̀ - Ẹgbẹ́ ajàfẹ́tọ̀ọ́ ẹni
- Kí ló ń dá ọlọ́pàá dúró láti gbé Rahmon Adedoyin àti ọmọ rẹ̀ relé ẹjọ́ lórí ikú Timothy Adegoke?
- Baba Suwe ti kú tipẹ́ ṣaájú kí gbogbo èèyàn tó mọ̀ - Àbúrò olóògbé
- Bàyìí ni èmi àti Abdulsalami ṣe ṣiṣẹ́ pọ̀ ba èròngbà sáà kẹta Obasanjo jẹ́ - Thabo Mbeki
- Èèmọ! Kí ló mú àwọn akẹ́kòó gírámà fìkanra dá bàǹtẹ́ ìyà fún DPO ọlọ́pàá l‘Ogun?
- Irọ́ ni pé TAMPAN àtàwọn òṣèré tíátà kò tọ́jú Baba Suwe lásìkò àìsàn, àwọn bẹbẹ ta ṣe rèé - Mr Latin
- Wo àwòrán àwọn gbajúmọ̀ òṣèré tó péjú síbi ìsìnkú Baba Suwe
- Awuyewuye bẹ́ sílẹ̀ lórí ìlànà ìsìnkú Baba Suwe, àwọn Alfa yarí
- Ìdí rèé ta ṣe fi pósí gbe Baba Suwe tó jẹ́ Mùsùlúmì - Aya rẹ̀ àkọ́fẹ́ ṣàlàyé
Ijọba apapọ sọ ninu iwe ipẹjọ naa pe iwadii awọn fi han pe awọn janduku naa lo wa nidii oniruru ipaniyan, ifipabanilopọ, ijinigbe atawọn iwa ọdaran mii lapa Ariwa Naijiria.
O ni awọn naa lo wa nidi ijinigbepawo, ati ijinigbe pẹlu erongba lati fi agidi fi obinrin fun ọkọ ti inu wọn ko yọ si, fifi ẹran jẹko, ifiyajẹni, ijinigbe awọn akẹkọọ, ati bẹẹ bẹẹ lọ.
Ikọ olupẹjọ sọ fun ile ẹjọ naa pe Aarẹ Muhammadu Buhari ti buwọlu erongba lati kede awọn janduku ọhun gẹgẹ bii agbesumọmi.
Lẹyin naa ni adajọ Taiwo Taiwo gba ẹbẹ naa wọle to si kede ẹgbẹ Yan Bindiga, ẹgbẹ Yan Ta'adda atawọn ẹgbẹ mii kaakiri Najiria, paapaa lapa iha Ariwa Naijiria gẹgẹ bii ẹgbẹ agbesumọmi.
Ile ẹjọ naa tun kede gbogbo iṣe awọn janduku ọhun gẹgẹ bii eyii to lodi si ofin ni Naijiria.
Lẹyin idajọ naa ni adajọ Taiwo Taiwo wa paṣẹ ki ijọba apapọ fi ikede sita pe awọn janduku ti di agbesumọmi ni Naijiria ninu iwe iroyin meji to lamilaaka ati ninu iwe ti wọn ti n kede awọn iṣẹ kanṣe ijọba apapọ.














