Funmi Awelewa - N kò ní gbà kẹ lò mí tán, kẹ wá já mi jù sílẹ̀ bíi náírà márùn-ún àlòkù

Oríṣun àwòrán, funmiawelewa/Instagram
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn olólùfẹ́ Orijafunmi Awelewa, lọ tí ń janu lójú òpó Instagram láti gbé sẹ́yìn gbajúgbajà òṣèré olólùfẹ́ wọn, tó sọ̀kò ọ̀rọ̀ lu àwọn akẹ́gbẹ́ rẹ̀.
Àwọn akẹẹgbẹ́ rẹ̀ yìí ló ní wọ́n fẹ́ràn láti má sanwó iṣẹ́ tí wọ́n bá bẹ akẹ́gbẹ́ wọ́n láti kópa nínú sinimá agbéléwò.
Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe kọ́ soju òpó instagram rẹ̀, "ṣe ẹrí àwọn akẹ́gbẹ́ wa nínú eré tíátà, wọ́n fẹ́ràn láti máa bá àwọn ènìyàn ṣe, tí wọ́n bá rí àǹfààní lọ́dọ̀ ẹni náà ní.
- Látilẹ̀ ni mo ti fẹ́ràn orin ìjọ Kérúbù àmọ́ ẹlẹ́sìn mùsùlùmí àti krìstẹ́nì ni mí- Qdot
- Àwọn òṣèré Nollywood tí wọn ò sí lóri amóhùmáwòrán mọ́
- Iṣẹ́ ọpọlọ ló yẹ ká ṣe nínú tíátà, kìí ṣe àfihàn ara bíbó àbí ìhòòhò wa - Binta Mọgaji
- Kí ló mú omijé jáde lójú Lateef Adedimeji?
- Àwọn òṣèré tó ti bàjẹ́ láti ilé, ló kó ìbàjẹ́ wọ agbo tiata débi a'ṣọ ìhòòhò - Dele Odule
- Ẹ má jẹ́ kí ayélujára tàn yín jẹ́, mẹ̀kúnnù lọ̀pọ̀ àwa òṣèré tíátà - Iyabo Ojo
Ọmọ Iya mi jà f'órí rẹ̀. Awọ́n ènìyàn fẹ́ran láti lo ènìyàn, kì wọn sì já jù sílẹ̀ bí náírà márùn-ún àlòkù"
Orijafunmi ṣàlàyé pé kí gbogbo àwọn akẹ́gbẹ́ òun gbajumọ nǹkan tí yóò gbé oúnjẹ́ òòjọ́ wá sórí tábìlì wọ́n, nítorí lẹ́yìn ó rẹyìn, àwọn àti ẹbí nìkan ni yóò kojú nnkan tó bá jẹyọ.

Oríṣun àwòrán, funmiawelewa/Instagram
Ó fi kú pé kò sí anfaani kankan nínú kí ènìyàn jẹ́ ìlúmọ̀ọ́ká lai ni kọ́bọ̀ lápò.
Ó wá ké sí àwọn akẹ́gbẹ́ rẹ̀ pé bí wọ́n bá pe oun si iṣẹ́, kí wọ́n ṣetán láti sanwó isẹ́ òun.
Gbajúgbajà òṣèré náà, tí ọ̀pọ̀ mọ̀ sí Morili ni, ọ̀pọ̀ àwọn tó wà lókè kò ṣetán láti fà àwọn tó wà nílẹ̀ sókè, orí ara wọn nìkan ni wọn ń dù.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Wo ilúbìnrin tí wọn ti ń ní ìbálòpọ̀, bímọ̀ láì ní ọkọ
- Ọlọ́pàá àti ológun kò ní lójú àánú mọ́ fáwọn abàlújẹ́, ìyàtọ̀ yóò wà - Buhari
- Ìpínlẹ̀ Eko ń gbàlejò Ààrẹ Muhammadu Buhari lónìí
- Ẹ̀yin tẹ̀ ń pè fún ìyapa Nàíjíríà, òmùgọ̀ pátápátá ni yín - Obasanjo
- Kàyééfì! Ìyàwó bímọ mẹ́wàá lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, ọkọ kò níṣẹ́ lọ́wọ́
- Sunday Igboho ní òun ṣetán láti dira fáwọn ọ̀dọ́ Ibarapa fún ìpèsè ààbò aráàlú
- Àṣìta ìbọn pa ọkùnrin kan ní Ilesa níbi táwọn afurasí ẹlẹgbẹ́ òkùnkùn ti fìjà pẹ̀ta
- Iléesẹ́ Twitter ti ń bá ìjọba Nàìjíríà sọ̀rọ̀ papọ̀- Alhaji Lai Mohammed
- Àjọ EFCC mú àwọn afurasí aàdọ́ta tó ń lu jìbìtì lórí ayélujára ní Ibadan
- Ọ̀gbìn igbó kìí ṣe irúgbìn èṣù, ẹ pa èrò àtijọ́ tì, oríṣun ọrọ̀ ajé ni - Akeredolu
Ọ̀pọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ló ti wá ń kín ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́yìn pé, ọ̀rọ̀ Funmi Awelewa jána, àwọn òṣèré tíátà mìíràn pẹ̀lú wà lára àwọn tó gbàrùkù tí nǹkan ti Funmi sọ.
Díẹ̀ lára àwọn tó kín Funmi lẹ́yìn lórí ọ̀rọ̀ náà rèé

Oríṣun àwòrán, funmiawelewa/Instagram

















