Ibada EFCC arrest: Àjọ EFCC mú àwọn afurasí oníjìbìtì lórí ayélujára àádọ́ta ní Ibadan

Oríṣun àwòrán, EFCC
Ajọ to n mojuto iwa ajẹbanu ni Naijiria, EFCC ẹka ti Ibadan ni ipunlẹ Oyo ti kede eeyan aadọta ti ọwọ wọn tẹ nilu Ibadan.
Lọjọ Eti, ọjọ kẹrin, osu kẹfa, ọdun 2021 ni wọn ko awọn afurasi naa.
Agbegbe Alaro Sango, Agbaje Ijokodo ati Apete Aladura niluu Ibadan ni ọwọ EFCC ti tẹ wọn.
- Orílẹ̀-ède 174 káàkiri àgbáyé ní ìwọ́de Yoruba Nation yóò tí wáyé ní June 12- Ẹgbẹ́ Yoruba One Voice
- Ìbínú ńlá ti mú Àǹjọ̀nú tó ń jẹ́ Emmanuel lọ....àwọn kan ń sọ̀fọ̀ Lucifa tó lọ- Okotie
- Ẹ̀yin Fulani, ẹ yàgò fún ilẹ̀ Yorùbá lásìkò yìí- Iba Gani Adams
- Alaafin Oyo, Oba Adeyemi yarí lórí isẹ̀lẹ̀ ìsekúpani tó wáyé ní Igangan
- Ẹ̀yin olóṣèlú, ẹ má fi ìṣẹ̀lẹ̀ ìpànìyàn Igangan dá ìjà ẹlẹ́yàmẹ̀yà sílẹ̀- YWG
Adari ẹka iroyin ati ifitonileti fun ajọ EFCC, Wilson Uwujaren lo fi orukọ awọn afurasi naa sita bayii.
Wilson ni awọn mẹrinlelọgbọn ninu wọn ni wọn ti fidi ẹsun naa mulẹ̀ fun pe wọn jẹbi.
Awọn naa ni: Badmus Abeeb, Ibrahim Ahmed, Adeyemo Babatunde, Abdulrashid Ajagbe, Olajide Okiki Peter, Hassan Yusuf Atanda, Yusuf Olasupo Salaudeen, Bello Ahmed Bamidele, Adewale Damilola Tosin, Kolawole Yusuf Olawale, Nicholas Ferdinand, Keshiro Olanrewaju, Falana Victor Dapo, Abogunrin Emmanuel, Bosun Tomiwa Tunde, Shelter Chibundo, Banjoko Idris, ati Adebayo Akorede.

Oríṣun àwòrán, @EFCC
Awọn to ku ninu wọn ni: Awoyinka Afeez Ayodeji, Afonja Olarenwaju, Akingbade Taofeek, Ezekiel Adekunle, Ganiyu Sodiq, Abioye Abiodun, Ogunbayo Daniel, John Timileyin, Ominiyi Daniel, Adeniyi Idris Sodiq, Joseph James, Adeyemi Segun Oluwaseun, Adeleke Rasheed, Saliu Tomiwa Rasheed, Itoro Edet Ime ati Oseni Nasirudeen.
Uwujaren ni EFCC ri awọn ẹru ofin gab lọwọ awọn afurasi to ku naa.
Bakan naa lo ni wọn yoo gbe awọn to ku lọ sile ẹjọ lẹyin ti iwadii ti wọn naa ba ti pari.
- Ìjọba ẹ ṣọ́ra! gbígbégilé ojú òpó Twitter tako ẹ̀tọ́ àwọn ọmọ Naijiria - Gómínà Ṣeyi Makinde
- Alaafin Oyo, Oba Adeyemi yarí lórí isẹ̀lẹ̀ ìsekúpani tó wáyé ní Igangan
- Ẹ̀yin iléesẹ́ ìròyìn gbogbo ní Nàìjíríà, Ẹ dẹ́kun líló 'Twitter' bí bẹ́ẹ̀ kọ́...- NBC
- Ìbínú ńlá ti mú Àǹjọ̀nú tó ń jẹ́ Emmanuel lọ....àwọn kan ń sọ̀fọ̀ Lucifa tó lọ- Okotie














