Baba Ijesha: Iyabo Ojo ní ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ti tú àṣírí báwọn oníwàkòtọ́ ṣe pọ̀ sí ní Nàìjíríà

Oríṣun àwòrán, other
Gbajumọ oṣere tiata, Iyabọ Ojo ti ṣalaye idi to fi lewaju iwọde lọ tako itusilẹ akẹgbẹ rẹ to wa lahamọ ọlọpaa ni Panti nilu Eko.
Iyabọ Ojo ṣalaye ọrọ yii ninu fidio kan tose lati ba awọn ololufẹ rẹ sọ loju opo Instagram rẹ.
Osere tiata lobinrin naa ni saaju asiko yii, ohun ti awọn kan gba lero ni lati gba ẹyinkule tu Baba Ijesha silẹ yala nitoripe o jẹ gbajumọ lawujọ ni tabi ọwọ awọn alagbara ati alẹnulọrọ kan wa lẹyin rẹ nigba naa.
- Iyabo Ojo fèsì lórí béèlì tí wọ́n fún Baba Ijesha
- Béèlì Baba Ijesha kò túmọ̀ sí ìdáláre, iṣẹ́ sì ń bẹ níwájú - Yomi Fabiyi
- Princess pàrokò ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ lẹ́yìn tí Baba Ijesha gba béélì
- Baba Ijesha gba béélì níléẹjọ́ Májísírétì, àmọ́ ọ̀rọ̀ kù kó tó jáde l’àhámọ́
- Ẹ fi Baba Ijesha sílẹ̀ fún mi, màá ṣe onídùróó rẹ̀ - Yomi Fabiyi
- Màá pe Kọ̀mísánà ọlọ́pàá Eko àti igbákejì rẹ̀ lẹ́jọ́ lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha - Amofin
- ''Àwa àgbààgbà òṣèré kò dákẹ́ lórí wàhálà láàrin Iyabọ Ojo ati Yomi Fabiyi nitori Baba Ijẹsha''
- 'Nígbá tí a rí Baba Ijesha lónìí ní Panti, ohun tójú wa rí, ẹnu kò lè sọ o!'
- Ṣé lóòtọ́ ni Iyabo Ojo ti bẹ Yomi Fabiyi lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha tó wà ní Panti?
O ni ko sẹni to ni ki Baba Ijẹsha maa wa sile o, ohun ti awọn fẹ ni pe wọn ko gbọdọ tu u silẹ lọna ẹburu, ti araye yoo wa maa beere pe nibo lo wa tabi ta lo gba beeli rẹ, lasiko ti ile ẹjọ ba pada sẹnu iṣẹ ni ipinlẹ Eko.
O jẹ ko di mimọ pe, oun ko lee wẹyin wo lori ọrọ naa nitori pe Baba Ijesha gbọdọ jẹjọ fun iwa aitọ to hu si ọmọdebinrin naa.
"Ohun to mu wa lọ si ọdọ awọn ọlọpaa lakọkọ lati gbe ohun wa soke tako beeli Baba Ijesha ni pe, wọn fẹ tu Baba Ijẹṣha silẹ, ki wọn si fi awuruju pa ina ọrọ naa mọ abẹ aṣọ.
Awọn ibeere ti a si bi ọlọpaa nigba naa ni pe, ta lo n paṣẹ yii, ki ni awọn ilana ti ofin n beere fun beeli rẹ nigba naa,'ta lo fẹ gba oniduro rẹ amọ ti a ko ri esi kankan."
Iyabo Ojo ni ohun ti awọn dide fun nigba naa ni pe, bi o ba tilẹ jẹ pe wọn yoo tu Baba Ijesha silẹ, o gbọdọ jẹ ọna to ba ofin mu ni, dipo ọna awuruju to ni wọn kọkọ fẹ fi ṣe nigba naa nitoripe ilumọọka lẹni ti ọrọ kan.
"Ohun to ja ju bayii ni pe wọn n tẹle ilana to yẹ dipo ti ọna irọ ti wọn fẹ lo tẹlẹ."
Iyabọ Ojo tun ṣekilọ fun awọn obi ati alagbatọ lati mojuto awọn ọmọ wọn daradara, lati daabo bo wọn lọwọ awọn agbaaya lọkunrin ati lobinrin ti wọn fi iwa ibajẹ fifi ibalopọ kotọ lọ awọn majesin lawujọ.
O ni ọrọ Baba Ijesha naa ti wa fihan bi awọn eeyan to to n hu iwa aṣemaṣe si ọmọde, awọn afipabanilopọ ati oniwa aitọ sawọn ewe, ṣe pọ si lorilẹede Naijiria.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Òkú jíndé nígbà tó ku ìṣẹ́jú péréte ti wọ́n yóò se ètò ìkẹyìn fun
- Àwọn nọ́ọ̀sí àti àwọn òṣìṣẹ́ mííràn tó darapọ̀ mọ́ ìyásẹ́lódì le gbà ìwé ìdádúró
- Ọwọ́ amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ sí Gómìnà Ogun ségi lórí ẹsùn jìbìtì $350,000
- Àwọn ọmọ Yahoo dènà de ẹ̀ṣọ́ EFCC tó fòru wọ̀lú l'Osogbo, nǹkan yan
- Àwọn nọ́ọ̀sí àti àwọn òṣìṣẹ́ mííràn tó darapọ̀ mọ́ ìyásẹ́lódì le gbà ìwé ìdádúró
- Nàìjíríà ti rí €4.2m gbà padà nínú owó tí James Ibori gbé- Malami
- Wo ìdí mẹ́fà tí ìjóba kò se tíì kápá Boko Haram
O wa salaye fun gbogbo awọn to n beere pe ṣe oun yoo ṣi ta ile oun, fi ṣe ẹjọ lori ọrọ Baba Ijesha pe, oun ṣetan lati ta ile oun.
Iyabo ni bi wọn ba fẹ ra ile naa nitori pe oniṣowo to fẹran owo loun, oun si setan ati ta ile naa to ba ti jẹ iye to tọna ni wọn ba fẹ raa.



















