Baba Ijesha: Amòfin Ogunlana ní kò tọ́ bí wọn ṣe fi béèlì Omiyinka kọ́ ọrùn ìyanṣẹ́lódì òṣìṣẹ́ iléẹjọ́

Oríṣun àwòrán, Baba Ijesha Instagram/Adesina Ogunlana Facebook
Gbajugbaja agbẹjọro to n ja fun ominira Baba Ijesha, Adesina Ademola Ogunlana ti sọrọ lori iha ti awọn ọlapaa kọ si ọrọ to sọ nipa Baba Ijesha.
Ogunlana, tii se alaga tẹlẹ fun ẹgbẹ awọn agbẹjọro nipinlẹ Eko salaye pe, se ni ẹrin n pa oun nipa bi awọn eeyan naa se n dọgbọn lati tako ofin.
Ogunlana wa fikun pe awọn ọlọpaa ti ni ki oun kọ lẹta si Kọmisana ọlọpaa pe ki wọn fun Baba Ijesha ni beeli kuro ni ahamọ.
- 'Nígbá tí a rí Baba Ijesha lónìí ní Panti, ohun tójú wa rí, ẹnu kò lè sọ o!'
- Davido sí Yomi Fabiyi: Mùmú ni ẹ́
- Ẹ̀sùn gbígbìyànjú láti wọ́lé sí ojú ara ọmọdé pẹ̀lú ìpá àtàwọn ẹ̀sùn mìí tí Baba Ijesha yóò jẹ́ rèé
- Bí àwọn gbajúmọ̀ ṣe pín rèé lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha
- Iyabo Ojo gbé fídíò jáde nípa bí ọwọ́ ṣe tẹ Baba Ijesha
- Orí yọ ẹ́ o Baba Ijesha tí mi ò rí fídíò èpè tí wọ́n ní ò ń ṣẹ́, ǹkan tí mi ò bá ṣe fún ẹ... - Iyabo Ojo
- Iyabo Ojo fi ẹ̀hónú hàn ní àgọ́ ọlọ́pàá Panti láti tako béèlì Baba Ijesha
"Amọ igbesẹ ti wọn n beere naa ya mi lẹnu nitori ilana ti ko nitumọ lasan ni wsn ni ki n tẹle, ko wulo rara.
Mo si ti sọ fun igbakeji Kọmisana ọlọpaa Adegoke to beere lẹta naa pe se lo n tẹti abala kan ninu ero awọn araalu lori isẹlẹ naa.
Mo si sọ fun pe ẹnikẹni to ba jẹ asaaju gbọdọ ni ọkan akin ati igboya lati sọ ati se ohun to tọ nigba gbogbo, ko maa si dabi Pọntu Pilatu to mọ ohun to yẹ ko se lasiko igbẹjọ Jesu, amọ ti ko se e."
Agbẹjọro naa ni Pọntu Pilatu mọ ohun to yẹ ko se amọ se lo n fọ ọwọ rẹ kuro ninu igbẹjọ Jesu, to si jẹ ki wọn kan mọ agbelebu,eyi to fi n tan ara rẹ jẹ.
O ni oun tun sọ fun pe ko lọ ba ọga rẹ pe ki wọn se ohun to yẹ lati se lori ọrọ Baba Ijesha, ki wọn ma si se tẹti si ero araalu lasan.
Awọn ọlọpaa n tẹle abala kan ero araalu lori ọrọ Baba Ijesha
"Lootọ ni ero araalu se pataki lootọ amọ ko se pataki to ohun to yẹ labẹ ofin ati ohun ti ofin sọ.
O n salaye fun mi pe awọn ri pe afurasi naa se asemase pẹlu ọmọde ni awọn ko fi lee gba beeli rẹ gẹgẹ bi ofin se sọ.
Mo si ni se ofin tipinlẹ Eko lo n sọ, se ofin tipinlẹ Eko ga ju ofin apapọ ilẹ wa lọ ni? rara o, lootọ ni ko ga ju ofin Naijiria lọ."
Amofin Ogunlana ni ọrọ Baba Ijesha kọja boya o ba ọmọde se asemase tabi bẹẹkọ, ohun to wa nilẹ ni pe ka tẹle ohun ti ofin Naijiria sọ lori ọrọ naa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Àwọn olùwọ̀de Yoruba Nation mú afurasí òṣìṣẹ́ DSS níbi ìwọ́de l‘Osogbo
- Shehu Sani fi olùwọ́de Yoruba Nation ṣe ẹlẹ́yà torí òjò tó tú wọn ká
- A ti ṣe iṣẹ́ ribiribi lórí ètò ààbò láti ìgbà tí a ti gorií àléfà- Ààrẹ Buhari
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá rí ọmọ oṣù kan he lẹ́ba ọ̀nà lẹ́yìn tí wọ́n gbé e sọnù l'Eko
- Kò sẹ́ni tó lè ní kí n má yan àwọn Baálẹ̀ nílùú Akure- Ọba Aladetoyinbo Aladelusi
O ni ọrọ ofin kọja pe boya a fẹran oju Baba Ijesha tabi iwa to hu amọ ohun to yẹ ka wo ni ẹtọ atawọn anfaani ti afurasi naa ni labẹ ofin, ka si tẹle.
"O ti foju han gbangba pe se ni wọn n fi ọwọ ọla gba Baba Ijesha loju, ti wọn si n sọ fun pe a tẹ ori rẹ ba, ta si fi ẹtọ rẹ du ọ dipo ka sẹ awọn alagbara to tako ọ."
Agbẹjọro naa ni awọn ti kọ lẹta ọhun, ti awọn si ti fun ọlọpaa Adegoke, ẹni to salaye pe awọn yoo wo boya ileẹjọ yoo sisẹ lọjọ Aje lati gbe Baba Ijesha rele ẹjọ.
"Maa pe Kọmisana ọlọpaa Eko, Odumosu lẹjọ"
"Eyi naa ko tọna rara nitori ko dara bi wọn gbe ẹjọ Baba Ijesha kọ ọrun awọn osisẹ ẹka eto idajọ to n wosẹ niran.
Mo sọ fun pe maa pe oun ati Kọmisana Odumosu lẹjọ, kii se pe mo n dunkooko mọ wọn ni nitori a ti kọja akoko to yẹ ka maa dirẹbẹ fun awọn osisẹ ọba to yẹ ko maa tẹle ofin.
Otitọ ọrọ ree, bi wọn ba si se tete se ohun to tọ, lo se dara si nitori gbogbo eeyan lo yẹ ko maa sọrọ soke lori ifiyajẹni, ko si yẹ ka duro de akoko ti yoo kan wa abi ẹbi wa."
Ogunlana ni ohun tawọn n beere ni pe ki wọn fi Baba Ijesha silẹ nitori awọn osisẹ ẹka eto idajọ ni awọn si n tẹsiwaju pẹlu iyansẹlodi wọn, ti ipade wọn pẹlu ijọba si tun fori sanpọn.
Amofin naa wa n beere pe ti Baba Ijesha ba jẹ ibatan awọn ọlọpaa yii, se wọn yoo se bi wsn ti se yii?
O wa rọ awọn araalu lati maa dagunla si iwa ifiyajẹni, ti wọn yoo si ni bawọn ba ti jiire, abusebuse nitori ori yeye nimogun, ti aisẹ lo pọ.
"Beeli ni ẹtọ ẹnikọọkan to ba jẹ afurasi, koda ko si ẹsẹ ti ko yẹ ki wọn mase gba beeli rẹ. Baba Ijesha kọ lo kọ ofin naa."
"Ẹrin n pa mi lori bawọn eeyan kan se n sọko ọrọ si mi tori Baba Ijesha"
Wayi o, amofin Ogunlana tun ti sọrọ lori bi awọn eeyan kan se n sọko ọrọ lu oun lori ayelujara nipa bi oun se n beere ẹtọ ofin fun Baba Ijesha.
O ni igbesẹ wọn naa ko sẹyin igbesẹ ti oun gbe lati lọ wo Baba Ijesha ni ahamọ, ti oun si kọwe pe ki wọn gba beeli rẹ ni ahamọ ọlọpaa.
Bẹẹ ba gbagbe, agbẹjọro naa ati Yomi Fabiyi pẹlu awọn lọya miran ni wsn bẹ Baba Ijesha wo ni ahamọ, ti wọn si n sọ fun awọn ọlọpaa pe o tọ ki wọn gba beeli rẹ.
Amọ lẹyin igbesẹ naa ni agbẹjọro Ogunlana kede loju opo ayelujara Facebook rẹ pe se lawọn eeyan kan n sọko ọrọ si oun fun atilẹyin gbangba ti oun n se fun afurasi naa.
"Awọn eeyan ni anfaani lati sọ ero ọkan wọn lori awọn iroyin ti oun ba gbe soju opo ibanidọrẹ oun ati fidio pẹlu.
Amọ mo n kilọ fun awọn to ba n sọrọ lori iroyin naa pe wọn yoo gbara gba bọnbu ni ilọpo mẹwa.
Ẹ ba fi ọbẹ ge mi, ma fun yin lesi nitori emi kii se agbẹjọro to n mu tii lasan, ẹ ro lẹẹmeji, kẹ to maa se ẹnu belebele si mi."






















