Deji Akure and Ondo Government: Irọ́ ni pé ìjọba fòfin dè mí láti yan àwọn Baálẹ̀ nílùú Akure- Ọba Aladetoyinbo Aladelusi

Oríṣun àwòrán, @Ojuasha
Deji ti ilu Akure, Ọba Aladetoyinbo Ogunlade Aladelusi ti sọ pe oun ni aṣẹ lati maa yan awọn Olu ati Baalẹ ni ariwa ati guusu Akure tako ọrọ ti ijọba ipinlẹ naa sọ pe ko ni irufẹ agbara bẹẹ.
Akọwe oriade naa, Adeyeye Michael, lo sọ ọrọ na ninu atẹjade kan to fi ṣọwọ si awọn akọroyin.
Atẹjade naa ni "Deji ti ilu Akure ti ri awọn iroyin kan to n lọ ninu awọn iwe iroyin pe ijọba ipinlẹ Ondo ti fofin de e lati yan awọn oloye ati Baalẹ."
- 'Ẹ wòó kò jọọ́, èmi kò lè so nọ́mbà fóònù mi mọ́ NIN tíjọba Nàìjíríà ń gbé kiri'
- 'Nígbá tí a rí Baba Ijesha lónìí ní Panti, ohun tójú wa rí, ẹnu kò lè sọ o!'
- ICPC ń wá ọkọ ọmọ Buhari àtàwọn méjì míì lórí ṣíṣe $65,000,000 kúmọ kùmọ
- Àwọn ọlọ́pàá fojú afurasí to ṣekúpa Iniubong Umoren hàn bí ó ti wọ káà ilẹ̀ lọ
"A fẹ ki o ye gbogbo eeyan pe irọ pata ni awọn iroyin naa ati pe awọn to kọ irufẹ iroyin bẹẹ gbe igbesẹ ọhun lọna ati ṣi awọn araalu lọna ni."
Wọn ni bo tilẹ jẹ pe awọn gba lẹta kan lati ọọfisi ileeṣẹ ijọba ipinlẹ Ondo to n ri si ọrọ ijọba ibilẹ ati oye jijẹ lori ọrọ naa to ti wa nile ẹjọ tẹlẹ, ile ẹjọ ti da ẹjọ naa nu.

Oríṣun àwòrán, @DailyPostNGR
Atẹjade ọhun ni lati igba iwasẹ ni Deji ti jẹ alaṣẹ lori ilẹ Akure ati awọn ilu kereje to wa ni agbegbe rẹ, Deji si ni ẹni to maa n yan awọn oloye ati Baalẹ lori awọn ilu naa.
Bo tilẹ pe awọn Baalẹ kan ti kọkọ gbe Deji lọ ile ẹjọ lori iṣẹlẹ to jọ mọ ọrọ oye jijẹ naa ṣaaju, atẹjade ọhun ni ile ẹjọ ti da ẹjọ naa nu, Deji si ni alaṣẹ lori gbogbo ilẹ Akure.
Ọjọ kẹtala, oṣu Karun un, ọdun yii ni iroyin kan gbode pe ijọba ipinlẹ Ondo ti paṣẹ fun Deji ti ilu Akure lati jawọ kuro ninu yiyan awọn Baalẹ.
Lara awọn ilu ti iroyin naa sọ pe Deji ko laṣẹ lati yan Baalẹ rẹ ni Ago Sonibare ni Ala/Ajagbusi, Eleyewo, Ago-Ajapada ni igbo Ofosu, Ago Tedibomi ni Ala/Ajagbusi, Agunla to wa ni Ayede-Ogbese, Ilado/Elemo ati ilu Isinigbo.
- Àwọn eèyàn kan fara gbọta níbi ìjà àwọn Aṣọ́bodè àti Ònífàyàwọ́ nígboro Iseyin lọ́jọ́ ọdún
- Ìjá tó ń lọ́ láàrin ilẹ̀ Israel átí Palestian kò bá wa lára mú, ó ń kọwálọ́minú- Ìjọba Naijiria
- Saudi Arabia, Iran àti Egypt wà lára orile-ede àgbáyé tó ga jùlọ láti fi ikú ṣe ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ lọ́dún 2020
- ''Àwa àgbààgbà òṣèré kò dákẹ́ lórí wàhálà láàrin Iyabọ Ojo ati Yomi Fabiyi nitori Baba Ijẹsha''
- Aàrẹ Joe Biden sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́ lórí ìja Isreal àti Palestine















