Custom and Smugglers Iseyin clash: Àwọn eèyàn kan fara gbọta níbi ìjà àwọn Aṣọ́bodè àti Ònífàyàwọ́ nígboro Iseyin lọ́jọ́ ọdún

Oríṣun àwòrán, others
Awọn eeyan kan fi ara gba ọta nibi ija awọn aṣọbode ati onifayawọ n'igboro Iṣẹyin l'ọjọ ọdun.
Eeyan mẹrin ọtọọtọ ni iroyin sọ wi pe wọn padanu ẹmi wọn si ọwọ ọta ibọn ni gbegbe Ọja Ọba nilu Isẹyin lọjọ ọdun Eid Fitri lasiko ti awọn aṣọbode ati awọn onifayawọ doju ija kọ ara wọn.
Bakan naa ni iroyin sọ pe ẹni kan fi ara pa yanayana nibi iṣẹlẹ naa l'Ọjọbọ.
- ''Àwa àgbààgbà òṣèré kò dákẹ́ lórí wàhálà láàrin Iyabọ Ojo ati Yomi Fabiyi nitori Baba Ijẹsha''
- Aàrẹ Joe Biden sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́ lórí ìja Isreal àti Palestine
- Ẹ̀yìn tí ẹ̀ ń pè fún Yoruba Nation, òpè ní yín, ẹ kò ní ìmọ̀- Ladoja
- Wo àwọn ìpínlẹ̀ tó kéde àfikún ọjọ́ ìsinmi ọdún ìtúnu awẹ̀ síi
- Irọ́ ni pé àwọn ajínigbé ń bèèrè fún N30m láti tú pásítọ̀ Deeper Life sílẹ̀- ọmọ pásítọ̀
- Ṣé ǹkan oṣù rẹ ń dà hìì hìì lẹ́yìn tóó gba abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19? Ẹ gbọ́ tuntun lẹ́nu àwọn Dókítà
Iroyin fi idi ẹ mulẹ wi pe ibi ajọyọ ọdun itunu awẹ ni awọn eeyan yii wa ki wọn to ṣe kongẹ iku ojiji.
Arakunrin kan to jẹ olugbe ilu Isẹyin, Kehinde Akinsola sọ fun awọn akọroyin pe "aburo oun wa ni agbegbe Ọja Ọba lasiko ti iṣẹlẹ naa waye" gẹgẹ bi o ṣe n ke si ijọba lati gbe igbesẹ ni kiakia.

Oríṣun àwòrán, others
Nibayii, Asẹyin ti ilu Isẹyin, Oba Dr. Abdulganiy Adekunle Salau, Oloogunebi-Ajinese I ti kilọ fun ileeṣẹ aṣọbode lati sun sẹyin ni iwọn kilomita ogoji si ilu naa, bẹrẹ lati ẹnu ibọde to n bẹ ni Ayegun.
Ninu atejade ti wọn fi ranṣẹ si awọn akọroyin l'Ọjọbọ, Ọba alade naa ṣe apejuwe ṣiṣe iku pa awọn ọdọ lọjọ ọdun gẹgẹ bi iṣẹlẹ aburu ti ko gbudọ ṣẹlẹ mọ lọjọ iwaju.

Oríṣun àwòrán, others
Ẹwẹ, Oba Dr. Abdulganiy parọwa si awọn eeyan ilu lati fi aye gba alaafia gẹgẹ bi o ṣe n jẹjẹ wi pe awọn to ṣiṣẹ ibi naa ko ni ọ lai fi oju wina ofin.
- Ṣé lóòtọ́ ni Iyabo Ojo ti bẹ Yomi Fabiyi lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha tó wà ní Panti?
- Ohun tí mo fẹ́ ṣe fún ẹbí ẹ̀gbọ́n mí, Dare Adeboye rè é ... -Leke Adeboye
- Obìnrin ẹni ọdún 67 di àwátì lásìkò tó ń lọ sí ìṣọ́ òru
- Àjọ́ CAN pàṣẹ ètò àdúrà ọlọ́jọ́ mẹ́tà fún Naijiria ní May 28 sí 30, ẹ wo kókó àdúrá...
- Wo bí wọ́n ṣe kírun ìtúnu àwẹ̀ Ramadan 2021 ní Makkah àti Medina ní Saudi lónìí
- Òpó iná ẹ̀lẹ́ńtíríkì daṣẹ́rú, ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà wà lókùnkùn













