Eid Al Fitri Public holidays: Wo àwọn ìpínlẹ̀ tó kéde àfikún ọjọ́ ìsinmi ọdún ìtúnu awẹ̀ síi

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Awọn ipinlẹ kan lorilẹ-ede Naijiria ti ṣafikun ọjọ isinmi fun ọdun itunu aawẹ Ramadan ti 2021 siwaju sii.
Awọn ipinlẹ naa fi oni ọjọ Eti, ọjọ kẹrinla, oṣu karun un kun ọjọ meji ti ijọba apapọ kọkọ kede tẹlẹ, iyẹn ọjọru, ọjọ kejila ati ọjọbọ, ọjọ kẹtala, oṣu karun un.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
- Ṣé ǹkan oṣù rẹ ń dà hìì hìì lẹ́yìn tóó gba abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19? Ẹ gbọ́ tuntun lẹ́nu àwọn Dókítà
- Irọ́ ni pé àwọn ajínigbé ń bèèrè fún N30m láti tú pásítọ̀ Deeper Life sílẹ̀- ọmọ pásítọ̀
- Lẹ́yìn táwọn kan kírun lánàá, àwọn míì ṣọdún ìtúnu àwẹ̀ lónìí Ọjọ́bọ̀ n'Ibadan
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ni akẹ́kọ̀ọ́bìnrin fásítì Akungba l'Ondo gbẹ̀mí ara rẹ̀?
- Saudi Arabia, Iran àti Egypt wà lára orile-ede àgbáyé tó ga jùlọ láti fi ikú ṣe ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ lọ́dún 2020
- Ọ̀gá àgbà ọlọ́pàá ní Nàìjíríà pàṣẹ ki wọn kó ọ̀pọ̀ ọlọ́pàá síta fún ìtúnu àwẹ̀
Gomian ipinlẹ Kano, Abdulahi Ganduje lo kọkọ kede pe oun ti fi ọjọ Eti kun isinmi awọn eniyan ipinlẹ naa ni eyi ti wọn yoo fi fi ọjọ mẹta sami ayẹyẹ ipari awẹ Ramadan tọdun 2021.
Ogbeni Muhammed Garba Shehu to jẹ kọmiṣọnna ifitonileti ati iroyin gbogbo fun ipinlẹ Kano lo kọkọ fi eyi sita.
Lẹyin naa ni ijọba ipinlẹ Jigawa naa kede itẹsiwaju isinmi pe ki ti ipinlẹ naa di ọjọ mẹta.
Hussaini Ali Kila to jẹ olori awọn oṣiṣẹ ni ipinlẹ Jigawa lo fi atẹjade sita lati kede isinmi ọjọ Eti kun eyi ti ijọba apapọ kede tẹlẹ.
Wọ́n ti kírun ọdún ìtúnu àwẹ̀ n'Ibadan
L'Ọjọru ni Imam agba ilẹ Ibadan, Sheikh AbdulGaniyu Abubakry Agbotomokekere le iwaju irun itunu awẹ ni gbagede Yidi to n bẹ ni gbegbe Agodi nilu Ibadan.
Igbakeji gomina ipinlẹ Ọyọ, Rauf Olaniyan ati Olubadan ilẹ Ibadan, Oba Saliu Adetunji wa lara awọn eeyan pataki to pejupesẹ sibi irun naa.
- Iyabo Ojo pé Yomi Fabiyi lẹ́jọ́, ìdí abájọ rèé
- Wo bí ìwọ́de Yomi Fabiyi nítorí ọ̀rọ̀ Baba Ijẹsha to wa ni àhámọ̀ ọlapàá ṣe n lọ nílùú Eko
- Ṣé èdì tàbí àsàsí leè sọ èèyàn di "Paedophile" tí kiní abẹ́ rẹ̀ kò ní gbé bì kan? - Elebuibon sọ̀rọ̀
- Eid al-Fitr: Wo àwọn ohun tó yẹ ki o ṣe sáájú ìrun Yidi fún ọdún ìtúnu ààwẹ̀
- Ẹ̀yin ọmọ Naijiria, ẹ gbé ohùn àdúrà sókè nítorí ètò ààbò Naijiria - Buhari
- Ogójì èèyàn ti pàdánù ẹ̀mí wọn nítorí ìjà tó ń wáyé láàrín Israel àti Palestine ní Lod
- Ààwẹ̀ Ramadan ṣì tẹ̀síwájú dí Ọjọ́ọ̀rú, a kò tíì rí òṣùpá- Supreme Council (NSCIA)

Adura yii waye t'oun ti bi ajọ to n mojuto ọrọ ẹsin Islam lorilẹede Naijiria, 'Nigerian Supreme Council for Islamic Affairs (NSCIA)' ṣe paa laṣẹ wi pe ki awẹ Ramadan tẹsiwaju nitori osupa Shawal ko yọ ni alẹ ana.
Aṣẹ yii lo mu ki awẹ di ọgbọn.

Ọrọ kan ti wọn fi lede loju ọpọ ikansiraẹni Facebook Sheik Agbotomokekere lana lo kede rẹ wi pe awẹ Ramadan ti pari l'ọjọ Iṣẹgun, ọdun itunu awẹ yoo si waye l'Ọjọru.

Gẹgẹ bi ileri ti o ṣe, Sheik Agbotomokekere le iwaju awọn Musulumi kan lọ si Yidi, ṣugbọn pupọ ninu awọn adari ẹsin bi i Aarẹ Musulumi ilẹ Yoruba, Edo ati ipinlẹ Delta, Alhaji Dawud Makanjuola Akinola De-Damak, gomina tẹlẹri nipinlẹ Ọyọ, Oloye Rashidi Ladoja ati awọn mii ko si nibi ipejọpọ naa.

Bo tilẹ jẹ wi pe awọn eeyan pọ nibi ipejọpọ naa, onka awọn to kirun ọdun itunu awẹ nibẹ ko to iye awọn to n wa tẹlẹri. Iredi sini wi pe awọn eeyan kan ṣi gba awẹ titi di oni.
Eleyii ki i ṣe igba akọkọ ti iru igbese yii yoo waye, asaaju ẹsin yii kede iru igbese yii ni ọdun mẹta sẹyin, botilẹ jẹ wi pe awọn alaṣẹ ni o yẹ ki awẹ tẹsiwaju.
- Kàyèéfì! Wo ìdí tí àlùfáà ìjọ Aguda fi ń kó ère ìṣẹ̀nbáyé pamọ́?
- Wo bí ìwọ́de Yomi Fabiyi nítorí ọ̀rọ̀ Baba Ijẹsha to wa ni àhámọ̀ ọlapàá ṣe n lọ nílùú Eko
- Davido sí Yomi Fabiyi: Mùmú ni ẹ́
- Ṣé lóòtọ́ ni Iyabo Ojo ti bẹ Yomi Fabiyi lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha tó wà ní Panti?
- Ohun tí mo fẹ́ ṣe fún ẹbí ẹ̀gbọ́n mí, Dare Adeboye rè é ... -Leke Adeboye
- Baba Ijesha yóò ṣì wà látìmọ́lé títí ilé ẹjọ́ yóò fi parí ìyanṣẹ́lódì- Kọmisọ́nà Ọlọ́pàá














