Eid-el-Fitri security: Ọ̀gá àgbà ọlọ́pàá ní Nàìjíríà pàṣẹ ki wọn kó ọ̀pọ̀ ọlọ́pàá síta fún ìtúnu àwẹ̀

Oríṣun àwòrán, @Nigeria Police
Ọga agba ọlọpaa lorilẹ-ede Naijiria, Alkali Usman Baba ti paṣẹ ti paṣẹ pe ki wọn da ọlọpaa sita kaakiri Naijiria lọpọ yanturu lọna ati mu ki okun abo o tubọ gbopọn lasiko itunu awẹ to wa lode.
Ninu ọrọ ti alukoro apapọ ileeṣẹ ọlọpaa, Frank Mba fi sita, ọga agba ọlọpaa ni Naijiria ti kan si gbogbo awọn amugbalẹgbẹ rẹ, awọn kọmiṣọnna ọlọpaa ni ipinlẹ pẹlu awọn lọgalọga lẹka ileeṣẹ ọlọpaa lati gbe igbesẹ gbogbo to ba yẹ fun idaabobo bo araalu lasiko ọdun yii.
- Òpó iná ẹ̀lẹ́ńtíríkì daṣẹ́rú, ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà wà lókùnkùn
- Wo bí wọ́n ṣe kírun ìtúnu àwẹ̀ Ramadan 2021 ní Makkah àti Medina ní Saudi lónìí
- Àjọ́ CAN pàṣẹ ètò àdúrà ọlọ́jọ́ mẹ́tà fún Naijiria ní May 28 sí 30, ẹ wo kókó àdúrá...
- Obìnrin ẹni ọdún 67 di àwátì lásìkò tó ń lọ sí ìṣọ́ òru
- Lẹ́yìn ìwọ́de Yomi Fabiyi, ọlọ́pàá sọ ìdí tí wọ́n kò fi gba béélì Baba Ijẹsha, àti ìgbà tó ṣe é ṣe kí wọ́n ó fi sílẹ̀
- Ẹni tó bá ní láàkàyè, a mọ ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn, àwà ti kọ lẹ́tà, èsì t'Ọ́lọ́pàá sì fún wa rèé - Yomi Fabiyi
Ọga ọlọpaa Usman Baba nilootọ ọrọ abo ti dagun lorilẹede Naijiria sibẹ kii ṣe ohun to kọja bibori.
Bakan naa lo tun fọkan awọn ọmọ Naijiria balẹ pe ileesẹ ọlọpaa labẹ idari oun ko ni ja wọn ni tan mọnnn nipa ririi daju pe ojuutu wa si ọrọ abo to mẹhẹ ni Naijiria.
O wa ro awọn ọmọ Naijiria lati fọwọsowọpọ pẹl'awọn ọlọpaa lọna ati tu aṣiri gbogbo awọn oniṣẹ ibi lawujọ pẹlu ibuba wọn.
Lori ipele kẹrin ilana igbogun ti ajakalẹ arun COVID-19 ni Naijiria, iyẹn Level-4 protocol ti ijọba apapọ ṣẹsẹ kede.
- Ohun tí mo fẹ́ ṣe fún ẹbí ẹ̀gbọ́n mí, Dare Adeboye rè é ... -Leke Adeboye
- Iyabo Ojo pé Yomi Fabiyi lẹ́jọ́, ìdí abájọ rèé
- Davido sí Yomi Fabiyi: Mùmú ni ẹ́
- Wo bí ìwọ́de Yomi Fabiyi nítorí ọ̀rọ̀ Baba Ijẹsha to wa ni àhámọ̀ ọlapàá ṣe n lọ nílùú Eko
- Ogójì èèyàn ti pàdánù ẹ̀mí wọn nítorí ìjà tó ń wáyé láàrín Israel àti Palestine ní Lod
- Òṣèré tíátà Yorùbá míràn tún kó sí gbaga ọlọ́pàá
- Ọmọdé méje àti olùkọ́ kan jẹ́ Ọlọrun nípè lẹ́yìn tí agbébọn ẹni ọdún 19 ṣíná ìbọn bolẹ̀ nílé ẹ̀kọ́ wọn
Ọga agba ọlọpaa lorilẹ-ede Naijiria naa rọ awọn ọga ọlọpaa ni ipinlẹ lati ṣiṣẹ tọ ilana tuntun naa lẹyin nipa ririi dajupe awọn eeyan ni ipinlẹ koOwa wọn tẹlẹ ilana ti ijọba apapọ gbe kalẹ lati dena ajakalẹ
COVID-19 lẹẹkan sii ni Nigeria.














