Ondo kidnap: Fowokemi Ogedengbe, ọmọ Pasitọ Deeper Life tí wọ́n jígbé l'Ondo ní àwọn ajínigbé kò tíì pe àwọn

Awọn ẹbi ati ara Pasitọ ijọ Deeper Life ti wọn jigbe lọ ni ilu Akure, Otamayomi Ogedengbe ni awọn ko i tii gbọ ohun kankan lati ọdọ awọn janduku to ji i gbe lọ.
Iroyin to lo ori ayelujara ni pe awọn ajinigbe ọhun beere fun ọgbọn miliọnu naira lalẹ Ọjọru nigba ti wọn pe ẹbi pasitọ naa.
Iroyin mii tiẹ sọ pe awọn janduku ajinigbe pawo naa sọ pe owo itusilẹ naa ko gbọdọ din ni ọgbọn miliọnu.
- Kí ló mú Yomi Fabiyi àti Iyabo Ojo máa sá aṣọ ìdọ̀tí ara wọn síta?
- Ohun tí mo fẹ́ ṣe fún ẹbí ẹ̀gbọ́n mí, Dare Adeboye rè é ... -Leke Adeboye
- Ọ̀gá àgbà ọlọ́pàá ní Nàìjíríà pàṣẹ ki wọn kó ọ̀pọ̀ ọlọ́pàá síta fún ìtúnu àwẹ̀
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ni akẹ́kọ̀ọ́bìnrin fásítì Akungba l'Ondo gbẹ̀mí ara rẹ̀?
- Lẹ́yìn táwọn kan kírun lánàá, àwọn míì ṣọdún ìtúnu àwẹ̀ lónìí Ọjọ́bọ̀ n'Ibadan
- Òṣèré tíátà Yorùbá míràn tún kó sí gbaga ọlọ́pàá
Ṣugbọn ọmọbinrin pasitọ naa, Fowokemi Ogedengbe sọ fun BBC Yoruba pe irọ funfun balau ni iroyin tawọn kan n gbe kiri.
Fowokemi ṣalaye pe ẹbi pasitọ Deeper Life ọhun ko ti gbọ lati ọdọ awọn ajinigbe titi di akoko yii.
Ọmọ baba naa ni: ''A ko mọ ibi ti awọn to kọ iroyin pe wọn ti tu u silẹ ti gbó iroyin naa.
Bi emi ṣe rii ka lori ayelujara niyẹn, amọ ko si otitọ kan ninu iroyin naa.
A ko mọ ibi ti baba mi wa bayii nitori awọn ajinigbe naa ko tii pe wa,'' Fowokemi lo ṣalaye bẹẹ.
O rọ awọn eeyan lati maa fi adura ran idile awọn lọwọ wi pe ki awọn janduku ajinigbe naa le fi olori ile wọn silẹ.
- Lẹ́yìn ìwọ́de Yomi Fabiyi, ọlọ́pàá sọ ìdí tí wọ́n kò fi gba béélì Baba Ijẹsha, àti ìgbà tó ṣe é ṣe kí wọ́n ó fi sílẹ̀
- Davido sí Yomi Fabiyi: Mùmú ni ẹ́
- Òṣèré tíátà Yorùbá míràn tún kó sí gbaga ọlọ́pàá
- Ọmọdé méje àti olùkọ́ kan jẹ́ Ọlọrun nípè lẹ́yìn tí agbébọn ẹni ọdún 19 ṣíná ìbọn bolẹ̀ nílé ẹ̀kọ́ wọn
- Ogójì èèyàn ti pàdánù ẹ̀mí wọn nítorí ìjà tó ń wáyé láàrín Israel àti Palestine ní Lod
Ọmọbinrin Pasitọ Ogedengbe, Fowokẹmi ni inu ipaya ati ibẹru ni awọn wa nitori awọn ajinigbe naa ko tii kan si wọn.
O ni baba oun ni ilera to si ni awọn oogun ti oun lo ni ojoojumọ, amọ lati igba ti wọn ti jigbe lọ yii awọn ko gbọ nkankan.
Ọjọ Kẹwaa, Oṣu Karun un ni wọn ji pasitọ Godwin Mayomi Ogedengbe lẹyin to pari isin ninu ile ijọsin rẹ ni nkan bi aago mẹsan an alẹ.
- Kí ló mú Yomi Fabiyi àti Iyabo Ojo máa sá aṣọ ìdọ̀tí ara wọn síta?
- Ohun tí mo fẹ́ ṣe fún ẹbí ẹ̀gbọ́n mí, Dare Adeboye rè é ... -Leke Adeboye
- Baba Ijesha yóò ṣì wà látìmọ́lé títí ilé ẹjọ́ yóò fi parí ìyanṣẹ́lódì- Kọmisọ́nà Ọlọ́pàá
- Obìnrin ẹni ọdún 67 di àwátì lásìkò tó ń lọ sí ìṣọ́ òru
- Àjọ́ CAN pàṣẹ ètò àdúrà ọlọ́jọ́ mẹ́tà fún Naijiria ní May 28 sí 30, ẹ wo kókó àdúrá...
- Wo bí wọ́n ṣe kírun ìtúnu àwẹ̀ Ramadan 2021 ní Makkah àti Medina ní Saudi lónìí















