Eid al-fitr 2021: Àwọn míì ṣọdún ìtúnu àwẹ̀ lónìí Ọjọ́bọ̀ n'Ibadan lẹ́yìn táwọn kan kírun lánàá

Oríṣun àwòrán, Other
Ọpọlọpọ awọn eekan ninu ọṣelu ati awọn Musulumi to gba awẹ di ọgbọn ọjọ lo pejupesẹ si awọn ọkanojọkan Yidi nilu Ibadan ati jakejado ipinlẹ Ọyọ lati ṣe ajọyọ ọdun itunu awẹ lonii.

Oríṣun àwòrán, Other
Lara awọn eeyan pataki to kopa nibi irun ọdun itunu awẹ ni Mọṣalaṣi nla to n bẹ ninu ọgba fasiti ilẹ Ibadan ni Gomina tẹlẹri nipinlẹ Ọyọ, Sẹnetọ Rasheed Ladoja, Sẹnetọ aarin gbungbun Ọyọ, Teslim Folarin.

Oríṣun àwòrán, Other
Sẹnetọ agbegbe ariwa Ọyọ, Abdulfatai Buhari, Kọmisana tẹlẹri fun ọrọ ayika nipinlẹ Ọyọ, Oloye Lowo Obisesan ati bẹẹ bẹẹ lọ.

Oríṣun àwòrán, Other
Irun ọdun itunu awẹ waye lonii lẹyin ti Imam agba ilẹ Ibadan, Sheik Agbọtọmọkekere ko awọn Musulumi kan ṣodi n'Ibadan lati ṣe adua itunu awẹ l'Ọjọru.
- Ohun tí mo fẹ́ ṣe fún ẹbí ẹ̀gbọ́n mí, Dare Adeboye rè é ... -Leke Adeboye
- Ikú kò m'ọmọdé, kò màgbà, ẹ gbàdúrà fún ìdílé mi àti aya pẹ̀lú ọmọ olóògbé- Pásítọ̀ Adeboye
- Ọkọ mi kò kú rárá- Arabinrin Temiloluwa aya olóògbé Dare Adeboye
- Wo bí wọ́n ṣe kírun ìtúnu àwẹ̀ Ramadan 2021 ní Makkah àti Medina ní Saudi lónìí
- Òpó iná ẹ̀lẹ́ńtíríkì daṣẹ́rú, ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà wà lókùnkùn
- Iyabo Ojo pé Yomi Fabiyi lẹ́jọ́, ìdí abájọ rèé
- Wo bí ìwọ́de Yomi Fabiyi nítorí ọ̀rọ̀ Baba Ijẹsha to wa ni àhámọ̀ ọlapàá ṣe n lọ nílùú Eko
Botilẹ jẹ wi pe irun naa waye ni Yidi to n bẹ ni agbegbe Agodi nilu Ibadan, awọn eeyan to kopa nibẹ ko pọ tọ iye awọn eeyan to kirun ọdun itunu.
Wọnyii ni aworan bi ọdun itunu awẹ ṣe lọ ni ilu Ibadan.

Oríṣun àwòrán, Other

Oríṣun àwòrán, Other

Oríṣun àwòrán, Other

Oríṣun àwòrán, Other

Oríṣun àwòrán, Other












