Oduduwa Nation: Ẹ̀yìn tí ẹ̀ ń pè fún Yoruba Nation, òpè ní yín, ẹ kò ní ìmọ̀ - Ladoja

Oríṣun àwòrán, Twitter
Gomina ipinlẹ Ọyọ tẹlẹ, Rasheed Ladọja ti kilọ fun awọn to n beere fun idadurọ orilẹede Yoruba, Oduduwa Nation lati jawọ nitori ibẹrẹ ogun ni yoo jẹ.
Ladọja lo sọrọ nibi adura Eid lasiko ọdun Ramada ni ilu Ibadan.
Ninu ọrọ rẹ, Ladọja ni ibeerẹ ogun ni ọpọlọpọ eniyan ma n mọ, wọn ki n mọ opin rẹ.
O fikun wipe awọn to n beere fun Oduduwa Nation ko mọ itunu rẹ ati ohun ti yoo jasi fun awọn eniyan.
- 'Nígbá tí a rí Baba Ijesha lónìí ní Panti, ohun tójú wa rí, ẹnu kò lè sọ o!'
- Saudi Arabia, Iran àti Egypt wà lára orile-ede àgbáyé tó ga jùlọ láti fi ikú ṣe ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ lọ́dún 2020
- Ṣé lóòtọ́ ni Iyabo Ojo ti bẹ Yomi Fabiyi lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha tó wà ní Panti?
- Irọ́ ni pé àwọn ajínigbé ń bèèrè fún N30m láti tú pásítọ̀ Deeper Life sílẹ̀- ọmọ pásítọ̀
- Ṣé ǹkan oṣù rẹ ń dà hìì hìì lẹ́yìn tóó gba abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19? Ẹ gbọ́ tuntun lẹ́nu àwọn Dókítà
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ni akẹ́kọ̀ọ́bìnrin fásítì Akungba l'Ondo gbẹ̀mí ara rẹ̀?
- Davido sí Yomi Fabiyi: Mùmú ni ẹ́
''Ko si ẹni to mọ bi ogun to bẹ silẹ ni Syria ṣe bẹrẹ, ti wọn si ti wa lẹnu rẹ fun ọpọlọpọ ọdun bayii lai tii si ọna abayọ si ogun naa, ti ọpọlọpọ ẹmi si ti ba iṣẹlẹ naa lọ''
''Adura to yẹ ki a maa gba ni wi pe ki Ọlọrun fun wa ni adari to dara lorilẹede Naijiria''.
Ladoja ni: ''Nigba miran Ọlọrun si le e fun wa ni awn adari ti ko dara lati koju awọn ipenija kọọkan, to ba jẹ igbayi ni a fẹ yapa kuro ni ara Naijiria, o yẹ ki a ro o daadaa pẹlu agbekalẹ to danmọran''.
''Ati wi pe ta lo sọ fun yin wi pe awọn ara ẹya Ariwa naa fẹ duro pẹlu Naijiria, awọn Guusu naa wa nibẹ ti wọn fẹ lọ, amọ suuru ni gbogbo rẹ gba''.

Oríṣun àwòrán, Twitter
''Ẹyin darandaran, dida ẹran kaakiri igboro ko bojumu mọ ni Naijiria''
Bakan naa ninu ọrọ rẹ ni Rasheed Ladọja ti kesi awọn darandaran lorilẹede Naijiria pe iṣe wọn ko ba ti igbalode mu mọ kaakiri agbaye.
Ladọja ni ko si ibi ti wọn ti n da ẹran kaakiri igboro, ti wọn si n ba oko oloko jẹ.
- Baba Ijesha yóò ṣì wà látìmọ́lé títí ilé ẹjọ́ yóò fi parí ìyanṣẹ́lódì- Kọmisọ́nà Ọlọ́pàá
- Ọ̀gá àgbà ọlọ́pàá ní Nàìjíríà pàṣẹ ki wọn kó ọ̀pọ̀ ọlọ́pàá síta fún ìtúnu àwẹ̀
- Lẹ́yìn táwọn kan kírun lánàá, àwọn míì ṣọdún ìtúnu àwẹ̀ lónìí Ọjọ́bọ̀ n'Ibadan
- Wo bí wọ́n ṣe kírun ìtúnu àwẹ̀ Ramadan 2021 ní Makkah àti Medina ní Saudi lónìí
- Òpó iná ẹ̀lẹ́ńtíríkì daṣẹ́rú, ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà wà lókùnkùn
- Ṣé lóòtọ́ ni Iyabo Ojo ti bẹ Yomi Fabiyi lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha tó wà ní Panti?
- Ohun tí mo fẹ́ ṣe fún ẹbí ẹ̀gbọ́n mí, Dare Adeboye rè é ... -Leke Adeboye
Ladọja ni opin gbọdọ deba dida ẹran kaakiri igboro nitori ipaniyan to n mu dani loore-koore.
O gboriyin fun awọn gomina kaakiri ipinlẹ ni Naijiria to ti sọ di ofin pe ko gbọdọ si dida ẹran kaakiri igboro mọ ni ipinlẹ wọn.
Amọ, o ni awọn gomina naa gbọdọ ri daju pe awọn eniyan n tẹle ofin naa, nipa fifi idi rẹ mulẹ ni awọn igberiko naa.














