#PantamiMustGo: Ajàfẹ́tọ́, Aisha Yesufu sọ ìdí tí kò fi lè so nọ́mbà fóònù rẹ̀ mọ́ nọ́mbà ìdánimọ̀ àpapọ̀ Nàìjíríà, NIN

Oríṣun àwòrán, Twitter/ aisha shehu
Ajafẹtọ ọmọniyan ni, Arabinrin Aisha Yesufu ti sọ pe ko sohun to jọọ o.
O ni oun ko le e so nọmba idanimọ apapọ ilẹẹ Naijiria, NIN mọ nọmba ibanisọrọ oun layelaye gẹgẹ bi ijọba apapọ Naijiria ṣe n fọnrere rẹ bayii.
Aisha Yesufu ni, siso oju opo numba ibanisọrọ oun mọ nọmba idanimọ apapọ NIN "yoo mu ki awọn iroyin to ṣe koko nipa oun wa ni ikawọ awọn elegbe ati alabaṣiṣẹpọ awọn agbesunmọmi" lorilẹ-ede Naijiria.
- 'Nígbá tí a rí Baba Ijesha lónìí ní Panti, ohun tójú wa rí, ẹnu kò lè sọ o!'
- Àwọn ọlọ́pàá fojú afurasí to ṣekúpa Iniubong Umoren hàn bí ó ti wọ káà ilẹ̀ lọ
- ICPC ń wá ọkọ ọmọ Buhari àtàwọn méjì míì lórí ṣíṣe $65,000,000 kúmọ kùmọ
- Àwọn eèyàn kan fara gbọta níbi ìjà àwọn Aṣọ́bodè àti Ònífàyàwọ́ nígboro Iseyin lọ́jọ́ ọdún
- Saudi Arabia, Iran àti Egypt wà lára orile-ede àgbáyé tó ga jùlọ láti fi ikú ṣe ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ lọ́dún 2020
- 'Ẹ wòó kò jọọ́, èmi kò lè so nọ́mbà fóònù mi mọ́ NIN tíjọba Nàìjíríà ń gbé kiri'
Aisha fi eleyi han loju opo Twitter rẹ nigba ti oun naa n da si ọrọ kan to n ja loju opo Twitter labẹ koko ọrọ #PantiMustGo.
Nibẹ ni awọn ero ori Twitter kan ti n pe fun iyọkuro nipo minisita fun ibanisọrọ lorilẹ-ede Naijiria, Isa Pantami.
"Ẹ jẹ ki n sọ ọ laifọtape pe, emi ko lee so nọmba idanimọ apapọ ilẹẹ Naijiria, NIN mọ nọmba ibanisọrọ mi o!
O san ki n kuku maa ni ẹrọ ibanisọrọ rara ju ki n finufindọ ko awọn iroyin to ṣe koko nipa oun wa ni ikawọ awọn elegbe ati alabaṣiṣẹpọ awọn agbesunmọmi #PantamiMustGo"
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
- Àwọn Olùkọ́ Akure pegedé lórí ètò Akomolede àti Aṣa lórí BBC Yorùbá
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ni akẹ́kọ̀ọ́bìnrin fásítì Akungba l'Ondo gbẹ̀mí ara rẹ̀?
- Ṣé ǹkan oṣù rẹ ń dà hìì hìì lẹ́yìn tóó gba abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19? Ẹ gbọ́ tuntun lẹ́nu àwọn Dókítà
- Irọ́ ni pé àwọn ajínigbé ń bèèrè fún N30m láti tú pásítọ̀ Deeper Life sílẹ̀- ọmọ pásítọ̀
- Ẹ̀yìn tí ẹ̀ ń pè fún Yoruba Nation, òpè ní yín, ẹ kò ní ìmọ̀- Ladoja
- 'Ẹ wòó kò jọọ́, èmi kò lè so nọ́mbà fóònù mi mọ́ NIN tíjọba Nàìjíríà ń gbé kiri'
Ipe fun iyọkuro nipo minisita fun ibanisọrọ lorilẹ-ede Naijiria, Isa Pantami n jo bi ina ẹrun lori ayelujara.
Eyi ko ṣehin nitori ọrọ iwasu kan to gbe kalẹ lawọn ọdun diẹ sẹyin ninu eyi to ti n ṣe atilẹyin fun awọn ẹgbẹ agbesunmọmi bii Al-Qaeda ati Taliban.
Amọṣa ileeṣẹ arẹ ti sọ pe ko sọrọ lori rẹ nitori nigba ti minisita Pantami sọ ọrọ yii ọmọde lo n ṣe e, o si ti yipada lasiko yii.













