Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá dóòlà ọmọ oṣù kan tí wọ́n gbé e sọnù l'Eko

Oríṣun àwòrán, Muyiwa Adejobi
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko ti doola ẹmi ọmọ oṣu kan ti wọn gbe ju si ẹba ọna nipinlẹ naa.
Ninu atẹjade kan ti alukoro ileeṣẹ ọhun, Muyiwa Adejobi fi ṣọwọ si BBC Yoruba, o ni wọn ri ọmọ jojolo naa ni orita ti ile epo Odun-Ade wa, iyẹn ni ibudokọ Orile.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, awọn eeyan kan to n kọja lẹba ọna ọhun lo ke si awọn agbofinro ni ẹka Orile lati wa wo ọmọ naa, lẹyin naa ni wọn gbe ọmọ ọhun lọ si ẹka ileeṣẹ ọlọpaa to n ri si ọrọ awọn obinrin, eyii to wa ni Ikeja.
- Kò sẹ́ni tó lè ní kí n má yan àwọn Baálẹ̀ nílùú Akure- Ọba Aladetoyinbo Aladelusi
- Èèyàn márùn ún kó sí gbaga ọlọ́pàá lórí ikú ẹ̀ni ọdún 42 kan l'Ẹ́dẹ
- 'Ẹ wòó kò jọọ́, èmi kò lè so nọ́mbà fóònù mi mọ́ NIN tíjọba Nàìjíríà ń gbé kiri'
- 'Nígbá tí a rí Baba Ijesha lónìí ní Panti, ohun tójú wa rí, ẹnu kò lè sọ o!'
- Àwọn ọmọ Yoruba láti ìpínlẹ̀ mẹ́jọ wọ́de fún ìdásílẹ̀ 'Yoruba Nation' ní ìlú Osogbo
- Ṣé ǹkan oṣù rẹ ń dà hìì hìì lẹ́yìn tóó gba abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19? Ẹ gbọ́ tuntun lẹ́nu àwọn Dókítà
Kọmiṣọna ọlọpaa ipinlẹ Eko, Hakeem Odumosu ti foju ganni ọmọ naa, o si ti paṣẹ pe ki wọn fun ni itọju to peye.
Kii ṣe igba akọkọ ree ti awọn eeyan ilu yoo gbe ọmọ sọnu nilu Eko ninu ọdun yii.
Lọjọ karundinlogun, oṣu Kẹta ọdun ti a wa yii, oninure kan pe akiyesi ileeṣẹ ọlọpaa si ọmọ kan ti wọn gbe sọnu lagbegbe Oko Oba, niluu Eko.
Ninu oṣu Kẹta kan naa ni wọn ri oku ọmọ jojolo miran lẹba ile iwosan Ayinke, to wa ni opopona papakọ ọkọ ofurufu, ni Ikeja niluu Eko yii kan naa.
Odumosu ti wa ṣeleri pe oun atawọn alabaṣiṣẹ oun yoo fọ ilu Eko mọ kuro lọwọ awọn iwa bii ki eeyan maa gbe ọmọ sọnu.
- Àwọn eèyàn kan fara gbọta níbi ìjà àwọn Aṣọ́bodè àti Ònífàyàwọ́ nígboro Iseyin lọ́jọ́ ọdún
- Ìjá tó ń lọ́ láàrin ilẹ̀ Israel átí Palestian kò bá wa lára mú, ó ń kọwálọ́minú- Ìjọba Naijiria
- Saudi Arabia, Iran àti Egypt wà lára orile-ede àgbáyé tó ga jùlọ láti fi ikú ṣe ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ lọ́dún 2020
- ''Àwa àgbààgbà òṣèré kò dákẹ́ lórí wàhálà láàrin Iyabọ Ojo ati Yomi Fabiyi nitori Baba Ijẹsha''
- Ẹ̀yìn tí ẹ̀ ń pè fún Yoruba Nation, òpè ní yín, ẹ kò ní ìmọ̀- Ladoja
- Irọ́ ni pé àwọn ajínigbé ń bèèrè fún N30m láti tú pásítọ̀ Deeper Life sílẹ̀- ọmọ pásítọ̀














