Corruption in Nigeria: Ojíṣẹ Ọlọ́run kan ní báwọn òbí ṣe ń jí owó ìlú kò, ní wọ́n ń fi lé ọmọ lọ́wọ́

Muhammadu Buhari

Oríṣun àwòrán, @MBuhari

Ojisẹ Ọlọrun kan ti woye pe ogun ti aarẹ Muhammad Buhari n gbe ti iwa ajẹbanu ko tii kun to rara.

Oludasilẹ ile ijọsin kan nilu Eko, Wolii Adegboyega Ajani lo woye ọrọ yii lasiko ipade akọroyin kan to ṣe lati sami ayajọ gbigbe ogun tiwa ajẹbanu lagbayee.

Ojisẹ Ọlọrun naa fikun pe, awọn elesinjesin gan ti kuna ninu gbigbe ogun tiwa ajẹbanu.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

"Ni gbogbo agbaye, tàwọn eeyan ba gbọ nipa iwa ajẹbanu, owo jiji nikan ni wọn maa n ro si eyi to jẹ asise.

O dabi igba ti eeyan n wa ojutu si isoro mẹta amọ ti onitọun gbajumọ ẹyọ kanṣoṣo, to si fi awọn isoro yoku silẹ.

Wolii Adegboyega Ajani atawọn ojisẹ Ọlọrun miran

Oríṣun àwòrán, Adegboyega Ajani

Idi ree to fi yẹ ka tete san sokoto wa ko le lati gbogun tiwa ajẹbanu naa.

Nigba to n sọrọ lori bi ajẹbanu naa ṣe n fẹju si, Wolii Ajani ni yoo nira diẹ kiwa ajẹbanu to kasẹ nilẹ ni Naijiria.

"Bi awọn obi ṣe n ko owo ilu, naa ni wọn n fi iwa àjẹbánu ọhun le awọn ọmọ wọn lọwọ, eyi ti ko ni jẹ ka tete ri ọna abayọ siwa ajẹbanu naa."

Àkọlé fídíò, Omolola Arohunmolase Welder: Mo ti fí iṣẹ́ 'Welder' gbayì láwùjọ, tó mo fi tọ́ ọmọ yanjú

Ojisẹ Ọlọrun naa ni gbogbo ẹka awujọ ni iwa ajẹbanu ti gogo pupọ, tàwọn oloselu atawọn gbajumọ si n ko owo ilu, ti wọn si tun n fi le awọn ọmọ wọn lọwọ.

Wolii Ajani wa rọ awọn ojisẹ Ọlọrun lati maa waasu tako iwa ibajẹ naa, ko le di ohun itan ni Naijiria

Ọ̀pọ̀ nkan tó n ṣẹlẹ̀ kò jẹ́ kí n gbàgbọ́ pé Naijiria wà ní abẹ́ ìdarí ẹnikẹ́ni - Wole Soyinka

Wole Soyinka

Agba onkọwe, Ọjọgbọn Wole Soyinka ti sọ pe, oun ko gbagbọ pe Naijiria wa ni abẹ idari ẹnikẹni.

O sọ eyi nibi ayẹyẹ ikojade iwe rẹ tuntun, 'Chronicles of the happiest people on earth', nilu Eko.

Ọjọgbọn Wole Soyinka ṣapejuwe ọdun 2020 gẹgẹ bi eyi to ti buru julọ ti oun mọ lorilẹ-ede Naijiria.

O ni kii ṣe nitori ajakalẹ aarun Covid-19 nikan, ṣugbọn ọpọlọpọ awọn iṣẹlẹ to waye, ati iha ti ijọba kọ si wọn.

O to ogoji ọdun ti Soyinka ti n kọ iwe naa, ko to o gbe jade lọdun 2020.

Àkọlé fídíò, 'Èmi gan máa ń béèrè lọ́wọ́ ara mi pé ta ni Wole Soyinka gangan'

Soyinka ni bi nkan ṣe ri bayii ni Naijiria, awọn ọmọ Naijiria ko mọ ibi ti wọn n lọ, tabi ibi ti irinajo wọn yoo pari si.

"Nnkan ti de ikorita ti eeyan ko ni idaniloju ibi to n lọ, ati ibi ti yoo pari rẹ si.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

"Bi mo ṣe sọ tẹlẹ, ọpọlọpọ nkan to n ṣẹlẹ ko jẹ kii eeyan o gbagbọ pe ẹnikẹni wa ni iṣakoso."

Soyinka sọ pe ọdun 2020 kii ṣe ọdun to dara rara fun oun, ni gbogbo ọna.