Liberia n wa ẹgbẹrun mẹfa tiṣa lati orilẹede Naijiria

Oríṣun àwòrán, European Photopress Agency
Orilẹede Liberia n wa olukọ lati orilẹede Naijiria ti yoo ṣe iranwọ fun orilẹede naa lẹka eto ẹkọ rẹ.
Aarẹ orilẹede Liberia, George Weah ni ẹgbẹrun mẹfa olukọ ni orilẹede oun nilo lati orilẹede Naijiria lati lee kun un lọwọ lẹka eto ẹkọ.
Aarẹ George Weah to wa ni orilẹede Naijiria lati ṣe ipade pẹlu Aarẹ Muhammadu Buhari ni ọjọ aje ni eleyi yoo kun ara adehun iranwọ to wa laarin orilẹede mejeeji.
Lẹyin ipade rẹ pẹlu aarẹ Buhari ni ilu Abuja, Aarẹ George Weah ni orilẹede Naijiria lo lee dide iranwọ fun orilẹede rẹ lori wahala naa.
Amọ ṣa, ibeere ti ọpọ n beere bayii ni wi pe ṣe orilẹede Naijiria lee ri ẹgbẹrun mẹfa olukọ ya orilẹede Liberia bayii pẹlu bii oun pẹlu ṣe n ba awọn iṣoro finra lori eto ẹkọ rẹ pẹlu?

Oríṣun àwòrán, @APCNigeria
Bi a ko ba gbagbe, laipẹ yii ni ijọba ipinlẹ Kaduna da nkan bii ẹgbẹrun marundinlọgbọn olukọ duro, iroyin eyi to kan kaakiri.
Awọn iroyin ti ẹ le nifẹ si:








