Attack on NDA: Iléeṣẹ́ ọmọogun Nàíjíríà ti dóòla Major Datong tí àwọn agbébọn jígbé lásìkò ìkọlù sí NDA

Oríṣun àwòrán, Others
Ileeṣẹ ikọ ọmọogun Naijiria ti doola ẹmi ọmọogun Major Christopher Datong ti awọn agbebọn jigbe lasiko ti wọn ṣekọlu si ọgba awọn ileẹkọ awọn ọmọogun, NDA.
Ninu atẹjade ti ileeṣẹ ọmọogun fi lede ni wọn ti kede pe awọn ti doola ẹmi rẹ ni alẹ Ọjọ Kẹtadinlogun, Osu Kẹsan, ọdun 2021.
Wọn ni awọn doola ẹmi rẹ lẹyin aṣẹ ti Olori ileeṣẹ ọmọogun ati awọn ọgagun paṣẹ pẹlu iranwọ ileeṣẹ ọmọogun ofurufu.
- Ẹgbẹ́ ọmọ bíbí Gúúsù Kaduna ní ìkọlù àwọn agbébọn sí NDA kìí ṣe ìyàlẹ́nu
- Ẹgbẹ́ ọmọ bíbí gúúsù Kaduna tún ti sọ̀rọ̀ pé ìkọlù sí iléeṣẹ́ ológun NDA kò jẹ́ ìyàlẹ́nu
- Àjàlú ńlá ń bọ̀ Buhari múra, màrìwò eégún lásán lo rí ní NDA - Fr Mbaka
- Ayo Ewebiyi Mama Oriki: Ọwọ́ Òbí, Ìjọba àti àwọn Ọba ni ìdágbàsókè Yorùbá wà lásìkò yìí
- Ẹ san N20bn náà fún Igboho kíákíá; Dáa padà! Ìjọba àpapọ̀ jùú sí ẹgbẹ́ Ilana Ọmọ Oodua
- Ojú ọjọ́ gbìgbóná jànyinjànyin ti kọjá kèrémí káàkiri àgbáyé
- Ọkùnrin kan dèrò àtìmọ́lé ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ewúrẹ́
- Yorùbá ẹ fura o! Ìwẹ̀fá ìjọba àpapọ̀ gbáà ní Fani-Kayode tó ń díbọ́n bí ọ̀kan lára wa
''Awọn ọgagun naa paṣẹ ki wọn doola ẹmi ọmọoogun Datong, ki wọn si mu gbogbo awọn agbebọn to lọwọ ninu iṣẹlẹ naa, boya ni aaye ni tabi oku wọn.''
''Lẹyin naa ni awọn ikọ ọmọogun sekọlu si agbegbe Afaka pẹlu ajọṣepọ ileeṣẹ ọtẹlẹmuyẹ ni Naijiria, DSS ati awọn ẹka eto aabo to ku.''
''Iwadii fihan, awọn ibi to ṣeeṣẹ ki awọn ajinigbe ko awọn eniyan ti wọn gbe si, paapaa ni agbegbe Afaka-Birnin Gwari.''
Ileeṣẹ ọmọgun fikun pe ọpọlọpọ awọn agbebọn naa lo fori fa iṣẹlẹ naa ni Ọjọ Kẹtadinlogun, Osu Kẹsan, ọdun 2021.
Bakan naa ni awọn agbebọn naa doju ibọn kọ awọn ikọ ọmọogun naa, amọ wọn ko bori wọn.
Ileeṣẹ ọmọogun ni bi o tilẹ jẹpe ọmọogun Dalong farapa diẹ ninu ikọlu naa, amọ alaafia ni o wa lẹyin to gba itọju ni ileewosan.
- Wo ìlú tó fẹ́ sọ àdúgbò kan lórúkọ aṣẹ́wó ọmọ Nàìjíríà, Eunice Osayande tí wọ́n pa
- Banki àpapọ̀ Nàìjíría ti pasẹ titi ojú òpó Aboki FX pa
- Ìyanṣẹ́lódì míràn kò ní pẹ́ bẹ̀rẹ̀ àyàfi tí Ijọba àpapọ̀ bá....- ASUU
- Kí ẹnikẹ́ni má gbé ìyá mi síta mọ́, mí o ní agbẹnusọ kankan mọ́- Sunday Igboho
- Judasi ìran Oduduwa ni Femi Fani-Kayode pẹ̀lú bó ṣe darapọ̀ mọ́ APC- Sheikh Gumi
- Wo iye ìgbà tí bàálù ìjagun ti já tó sì ṣekú pa àwọn ènìyàn ní Nàìjíríà
- Ẹ máa gbàá nìṣò, àwa Gómìnà ìhà Gúúsù f'ọwọ́ sí kí ìpínlẹ̀ má gba VAT
- Agbẹnusọ àjọ EFCC Wilson Uwujaren ti ṣàlàyé nǹkan tí ó ṣẹlẹ̀ sí ọ̀gá àjọ náà lósàn ọjọ́bọ
Nibayii, wọn ni Dalong ti wa ni ikawọ awọn adari ileẹkọ awọn ọmọogun naa.
Ileesẹ ọmọogun wa dupẹ lọwọ ajọ DSS, NAF, ileeṣẹ ọlọpaa Naijiria ati awọn ẹṣọ alaabo fun ipa ribiribi ti wọn ko lati sawari ọmọogun naa ti wọn si doola ẹmi rẹ.
Ọjọ Kẹrinlelogun, Osu Kẹjọ ni awọn agbebọn ṣekọlu si ileẹkọ awọn ọmọogun Naijiria, NDA, ti wọn si pa ọmọogun meji.















