ASUU Strike 2021: Ìyanṣẹ́lódì míràn kò ní pẹ́ bẹ̀rẹ̀ àyàfi tí Ijọba àpapọ̀ bá....- ASUU

Oríṣun àwòrán, @Others
Ẹgbẹ awọ̣n olukọ Fasiti ni Naijiria, ASUU ti kilọ wi pe o ṣeeṣe ki awọn bẹrẹ iyanṣelodi miran laipẹ.
Eyi ko ṣẹyin aimu adehun ti ijọba apapọ ṣe pẹlu awọn ẹgbẹ olukọ ṣẹ lati nkan bi osu mẹwaa sẹyin.
Oṣu kejila, ọdun 2020 ni ẹgbẹ oṣiṣẹ ASUU wọgile iyanṣẹlodi ti wọn gunle lẹyin ti ijoḅa apapọ ṣeleri lati ṣe agbeyẹwo gbogbo ibeere wọn ḷowọ ijọba.
- Ọkùnrin tó lẹ ''Super Glue'' mọ́ ǹkan ọkùnrin rẹ̀ láti rọ́pò ''condom'' ti dèrò ọ̀run
- Wo iye ìgbà tí bàálù ìjagun ti já tó sì ṣekú pa àwọn ènìyàn ní Nàìjíríà
- Mi ò sọ pé àwọn tó ń pè fún Yorùbá Nation kò yàtọ̀ sí Boko Haram o- Gbajabiamila ṣàlàyé
- ''APC yóò fún Goodluck Jonathan ní ànfàní láti dupò ààrẹ lọ́dún 2023 tó bá darapọ̀ mọ́ wa''
- ''Ìjọba, ẹ má da àwa tó ń ṣagbátẹrù Yorùbá Nation pọ̀ mọ́ IPOB''
Adari ẹka ẹgbẹ ASUU ni Benin, Ọjọgbọn Fred Esumeh lo sọ ọrọ yii lasiko to n ba awọn oniroyin sorọ wi pe o ṣeese ki iyanṣẹlodi miran bẹrẹ ni awọn ileewe fasiti kaakiri ni Naijiria nitori aibikita ijọba apapọ.
Esumeh ti ko sọ igba ti iyanṣẹlodi naa ma gberasọ sọ wi pe awọn n duro de abajade ipade pẹlu awọn adaari gbogboogbo ninu ẹgbẹ ASUU lati mọ igbesẹ ti awọn yoo gbe.
Ọdun 2020 ni Osu Kẹta ni awọn olukọ fasiti gunle iyansẹlodi nitori igbesẹ ijọba apapọ lori asunwon owo awọn oṣiṣẹ, to fi mọ awọn abuku to wa kaakiri awọn fasiti ni Naijiria.
Amọ, ẹgbẹ ASUU ni titi di asiko yii ijọba ko tii gbe igbese kankan lati parọ asuwọn owo IPPIS ṛe pẹlu asuwọn ibi ikọwopamọsi fun awọn Fasiti, ti wọn pe oruko rẹ ni ''University Transparency and Accountability Solution ''.
- A ti gbálé ati gbáta, kò sí ǹkankan lọ́wọ́ wa mọ́ ni a ṣe kígbe síta- Adebisi Aisha, Ọmọ Iyabo Oko
- Òní nilé ẹjọ́ yóò dájọ́ lórí awuyewuye owó oṣù àwọn dókítà pẹ̀lú ìjọba
- ECOWAS f'òfin de àwọn ológun tó dìtẹ̀ gbàjọba ní Guinea
- Iléẹjọ́ ti ní kí ìjọba Nàìjíríà san ogún bílíọ̀nù fún Sunday Igboho gẹ́gẹ́ bí owó gbà má bínú!
- Agbẹnusọ àjọ EFCC Wilson Uwujaren ti ṣàlàyé nǹkan tí ó ṣẹlẹ̀ sí ọ̀gá àjọ náà lósàn ọjọ́bọ
- Judasi ìran Oduduwa ni Femi Fani-Kayode pẹ̀lú bó ṣe darapọ̀ APC- Sheikh Gumi
Wọn ni ijọba apapọ mọọmọ se ifaṣẹyin nipa mimu ileri wọn ṣe nipa asunwọn owo University Transparency and Accountability Solution naa.
Bakan naa ni ijọba kọ lati san awọn ọmọ ajẹmọnu fun ẹka eto ẹkọ ni fasiti naa.
Kikọ lati fi iye owo to to ogoji bilionu naira silẹ lati fi tun awọn fasiti gbogbolowo ṣe.
Ẹwẹ, ẹgbẹ ASUU nipinlẹ Plateau ti fẹsun kan ijọba ipinlẹ naa labẹ aṣẹ ijọba gomina Simon Lalong jẹ awọn olukọ ni gbese ̣ni osu mẹrin odun 2020.
Bakan naa ni ijọba kuna lati gbe igbesẹ lori kikọ awọn ile igbe, iyẹn staff quarters fun awọn olukọ ni awọn ileewe fasiti, ni ipinlẹ naa.
- A ti gbálé ati gbáta, kò sí ǹkankan lọ́wọ́ wa mọ́ ni a ṣe kígbe síta- Adebisi Aisha, Ọmọ Iyabo Oko
- Kí ẹnikẹ́ni má gbé ìyá mi síta mọ́, mí o ní agbẹnusọ kankan mọ́- Sunday Igboho
- Mi ò sọ pé àwọn tó ń pè fún Yorùbá Nation kò yàtọ̀ sí Boko Haram o- Gbajabiamila ṣàlàyé
- Èmi tí wọ́n kọ́kọ́ pé ọkọ Bimbo kú gàn an ti di jálajála lórí ìròyìn burúkú náà- Jaye Kuti, ọ̀rẹ́ Bimbo Oshin
- Wo ọ̀nà méje tí o lè fi dáàbò bò ọmọ rẹ níbàyìí tí iléẹ̀kọ́ ti bẹ̀rẹ̀ padà















