Dudu Heritage: Ikú Ola Ibironke bá wa lójijì nítorí pé onínúure ni olówó orí Bimbo Oshin sí gbogbo wa- Rose Odika

Ọ̀pọ̀ awọn eeyan ni wọn ṣi n banujẹ lori iku Ola Ibironke Dudu Heritage.Ta ni Ola Ibironke, ọkọ Bimbo Oshin to dólògbé?
Awọn eeyan lorisirisi n jade sọrọ nipa bi o ṣe ṣelẹ ati ohun to fi ka wọn laya.
Gbajugbaja oṣere ni, Jaiye Kuti to jẹ ọrẹ timọtimọ fun aya oloogbe naa ni pe oloogbe naa ko ṣaisan kankan rara.
O ni ko si ẹni ti kò ní lọ ṣugbon ọjọ oni kaluku lo yato si ara wọn lati dero ọrun.
- Wo bí ọlọ́jọ́ ṣe dé fún Ola Ibironke, olówó orí Bimbo Oshin àti ibi tó parí iṣẹ́ sí
- Eèmọ̀ wọ̀lú, ẹni tó ń ta ọtí àti ògógóró gún Oníbárà rẹ̀ pa ní Osun!
- Atọ́kùn egúngún, ọmọ rẹ̀ àti èèyàn méjì dèrò àtìmọ́lè lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn ní mọ́ṣálááṣí
- Lóòtọ́ ni ìyá yìí bímọ méjì fún ọmọ rẹ̀ tó ń bá sùn, ohun tí a ṣe síi rèé - Àjọ NSCDC Kwara
- Femi Ojudu faṣọ iyí mọ́ Kayode Fayemi lára, Ó ní ojú ń gba òun ti fún ipò táwọn títì Ekiti wà
- Báàlù ìjagun kan já lulẹ̀ ní ìlú Buhari, ẹ̀mi àwọn aráàlú bọ́
Igba ti iṣẹlẹ yii sẹlẹ wọn kò mọ bí wọn ṣe fẹ pe Bimbo Oshin leyin to mu kí wọn pe òun fun iṣẹlẹ buruku naa.
''Emi gan an ti wọn pe ti di jatijati lẹyin ti won pe mi fun iroyin buruku naa".
Honorebu Olawale Abdul Majeed - Igbakeji olori oloṣelu Seyi Makinde ni ipinlẹ Oyonaa ba BBC Yoruba sọrọ nipa oloogbe pe o dabi ẹgbọn ti mo mọ lati okeere ni ti wọn jẹ eeyan daadaa.
O ni: Mo ti maa ń gbọ oruko lati okeere ni ẹyin igba ti wọn ku ni mo mọ wi pe awọn ni wọn jẹ Dudu Heritage.
Oladapo Olaide okan lara awon omo ẹgbẹ ibadan golf club sọrọ nipa oloogbe ilẹ kun.
O sọ pé oloogbe pe òun ni nnkan bii aago mẹwaa alẹ leyii to jẹ pe wọn ko pe ara wọn ni iru asiko bẹ ríi.
O pe lati fi ẹjọ nnkan to sẹlẹ ní golf club sùn òun leyii tó jẹ pé enikan níbi iṣẹ ni ó ṣẹ oloogbe ṣugbon òun àti àwọn ọmọ ẹgbẹ kọọkan bẹ́ẹ̀ tí ọrọ náà sí pada yanju.
Nibi tí wọn gbe gbero lati pe foonu ẹni tó ṣẹ oloogbe ki wọn le fi tó leti pé ija ti pari, sa deede lawọn kan ri pe oloogbe bu s'ẹrin lẹẹmeji ní Akin Funmilayo ti òun naa wa pelu wọn ṣe fura pe ẹjẹ ruru ni nnkan to ṣẹlẹ tí o sì gbabẹ lọ sọrun.
- Wo ọ̀nà méje tí o lè fi dáàbò bò ọmọ rẹ níbàyìí tí iléẹ̀kọ́ ti bẹ̀rẹ̀ padà
- Bí ọwọ́ wa kò bá tẹ àwọn tó lọ́wọ́ nínú ìkọlù sí ọgbà ẹ̀wọ̀n Kabba, a kò ní sinmi- Aregbesola
- Kókó nǹkan tí ẹgbẹ́ NINAS ń bèrè fún ní ibi ìpàdé UN General Assembly
- Èmi tí wọ́n kọ́kọ́ pé ọkọ Bimbo kú gàn an ti di jálajála lórí ìròyìn burúkú náà- Jaye Kuti, ọ̀rẹ́ Bimbo Oshin
- Sunday Igboho ránṣẹ́ tuntun nípa agbẹjọ́rò rẹ̀ ní Benin republic, Ó ní...
- Femi Ojudu faṣọ iyí mọ́ Kayode Fayemi lára, Ó ní ojú ń gba òun ti fún ipò táwọn títì Ekiti wà
Bakan naa ni ogbontarigi aṣere Yoruba ni, Rose Odika naa sọrọ pupọ nipa oloogbe Ola Ibironke.
Rose Odika ni pe Oloogbe naa jẹ ẹni to ni iwa tutu nigba aye rẹ.
O ṣapejuwe rẹ bii: Ẹni to maa ń ro ire kan eeyan nigba gbogbo to dẹ nifẹ si awọn kan iyawo rẹ .
Rose ni pe iku oloogbe ba gbogbo wa lojiji ti o si dun wa gidi gan an ni.

Oríṣun àwòrán, others
Wo bí ọlọ́jọ́ ṣe dé fún Ola Ibironke, olówó orí Bimbo Oshin àti ibi tó parí iṣẹ́ sí
Ohun ti eeyan ba fẹran ni mọni lara.
Ola Ibironke parí ìrìnàjò rẹ̀ síbi tó fẹ́ràn láti máa lọ, Ibadan Gulf Club
Egbẹ Ibadan Golf Club ti oloogbe Ola Ibironke jẹ eekan nibẹ ti fi ọrọ lede nipa iku ẹni wọn to lọ.
Ninu atẹjade naa ni wọn ti ni pe olowo ori Bimbo Oshin deede subu ni ki ọlọjọ to de.
Wọn ni nkan bii aago mẹjọ abọ alẹ ọjọ Aiku naa ni ìsẹlẹ yii ṣẹlẹ.
Koda, wọn ni Dudu Heritage wa pẹlu awọn ọrẹ rẹ ni gbagede golf club ni Ibadan ni lasiko ti ọlọjọ kan ilẹkun, bẹẹ ko si ẹni to ri ti ọlọjọ ṣe.
- 'Màmá mi, Iyabo Oko ti ní "Left Stroke" ní fọ́tò wọ́n ṣe rí bẹ́yẹn o àmọ́...'
- Sunday Igboho ránṣẹ́ tuntun nípa agbẹjọ́rò rẹ̀ ní Benin republic, Ó ní...
- Ẹ dákun ẹ ran Iyabo Oko lọ́wọ́, ìyá ti ń ṣàárẹ̀ láti ọdún márùn ún sẹ́yìn, o ti kọjá agbára wa- Foluke Daramola Salako
- Ṣọ́ọ̀ṣì wó pa èèyàn méjì ní Taraba, àwọn míràn farapa
- Wo iye kọ́ńdọ́mù táwọn ọmọ Nàìjíríà fi ń ṣara rindin lọ́dún
- Lébìrà tó jí iriniṣẹ́ iná mọ̀nàmọ́ná a fi ẹgba àtòrì méjìlá ṣara rindin kó lè kọ́ ẹ̀kọ́
- Okòòwò márùn ún tí o lè bẹ̀rẹ̀ nínú ilé rẹ̀
- Wo bí Pásítọ̀ Adeboye, Wòlíì Iginla ṣe ń dárò ikú akẹgbẹ́ wọn David Yonggi Cho
Awọn ẹgbẹ Dudu Heritage sọ pe wọn sare gbe akọni ọkunrin óhun lọ sile iwosan ki wọn to ni ẹpa ko boro mọ.
Koda, wọn ni ilaji ni asia yoo wa nibẹ ati pe ko ni si eto idaraya kankan lasiko yii lati fi ṣe ẹyẹ fun un.
Yoruba bọ wọn ni ọjọ a ba ku laa di ere. Bi iroyin iku gbajugbaja to n gbé iṣẹ́ olórin síta tó ṣáláìsí, Ola Ibironke ti ọpọ mọ si Dudu Heritage Production ṣe jade ni ọpọ oṣere ti n ṣe idaro.
Ẹwẹ, aworan oloogbe to ṣalaisi yii ko fibẹ wọpọ loju opo awọn oṣere, dipo bẹẹ aworan akẹgbẹ wọn Bimbo Oshin ni ọpọ wọn n fọn sori ayelujara lati baa kẹdun tori oun ni o kangun si wọn gangan.
Eyi ni awọn ololufẹ awọn oṣere ri ti wọn n beere pe ṣebi ọkọ rẹ lo ku, ewo ni aworan rẹ ti gbogbo oṣere wa n gbe saye.
Wo àwọn òṣèré tó ń fi àwòrán Bimbo Oshin kẹ́dùn ikú Dudu Heritage
Iroyin taa gbọ ni pe lọdun 2005 ni Ola Ibironke gbe gbajugbaja oṣere Bimbo Oshin niyawo.
Lara awọn oṣere akẹgbẹ Bimbo to n kii ku idaro Dudu Heritage niyi ti ọpọlọpọ wọn n gbadura fun oun ati idile wọn ti wọn si n gbaa niyanju lati mu ọkan le.

Oríṣun àwòrán, Lizzy Anjorin
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 1

Oríṣun àwòrán, Opeyemi Aiyeola

Oríṣun àwòrán, Seilat

Oríṣun àwòrán, Mercy Aigbe
O ka Faithia Balogun lara to bẹẹ to jẹ pe aworan ẹkun lo fi si oju opo tirẹ.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 2

Oríṣun àwòrán, Opeyemi Aiyeola



















