Poor roads in Ekiti state: Femi: Ká yọ tòṣèlú kúrò, Fayemi, àwọn òpópónà Ekiti ti di ẹgẹrẹmìtì, Babafemi Ojudu làá mọ́ Gómìnà Fayemi

Oríṣun àwòrán, other
Ọrọ oṣelu nipinlẹ Ekiti tun ba ibomiran yọ pẹlu bi o ṣe fẹ jọ pe, awọn eekan ẹgbẹ oṣelu naa meji ti n ta si ara wọn bayii.
Kayọde Fayẹmi ni gomina ipinlẹ Ekiti, ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC ni. Ọkan lara awọn to jẹ aṣiwaju lagbo oṣelu ni Babafẹmi Ojudu jẹ, ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC naa ni.
Ireti ọpọlọpọ onwoye ni pe o yẹ ki ọrọ awọn mejeeji ye ara wọn, amọṣa eyi ko fẹ da bi ẹni pe o n ri bẹẹ lọwọ.
- Sunday Igboho ránṣẹ́ tuntun nípa agbẹjọ́rò rẹ̀ ní Benin republic, Ó ní...
- Kókó nǹkan tí ẹgbẹ́ NINAS ń bèrè fún ní ibi ìpàdé UN General Assembly
- Ayẹyẹ ọdun Igogo gbérasọ ni ipinlẹ Ondo, ẹ wo bí ti ọdún yìí ṣe lọ
- Akeredolu yan Deji Akure gẹ́gẹ́ bi alága ìgbìmọ̀ àwọn ọba ni Ondo
- Wo ọmọ Nàìjíríà mẹ́fà tí UAE ń wá lórí ẹ̀sùn ṣíṣe àtìlẹ́yìn owó fún Boko Haram
Atẹjade kan ti Ọgbẹni Fẹmi Ojudu fi sita lọjọ Iṣẹgun lo ti n wọ Gomina Kayọde Fayẹmi atijọba rẹ pe wọn ko karamasiki ipo awobọkanjẹ tawọn opopona to wa ni ipinlẹ naa wa.
Ninu atẹjade naa, Ọgbẹni Ojudu ni oun ko lee dakẹ bi o tilẹ jẹ pe awọn kan lee maa ṣi ọrọ oun tumọ loun fi n pariwo lati pe akiyesi gomina Kayọde Fayẹmi ati ijọba rẹ si ipo arigbarimu ti awọn opopona wa ni ipinlẹ naa.
Femi ni: "Ipo ti awọn opopona ni ipinlẹ Ekiti wa n ba eeyan lọkan jẹ. Mo wa nibẹ lopin ọsẹ to kọja n ko si fẹrẹ lee gba ohun ti oju mi n ri gbọ. Gbogbo opopona igboro ati awọn ti marosẹ to wọle tabi jade ni ipinlẹ naa ni wọn ti di ẹgẹrẹmiti.
Ojudu fi kun un pe asiko to ki Gomina Fayẹmi o kede aṣẹ nnkan o fara rọ lẹka ipese ohun amayedẹrun ni ipinlẹ naa lati lee tubọ mojuto ẹka naa nitori pe iṣoro ati idojukọ tawọn olugbe ipinlẹ Ekiti maa n dojukọ bi ojo ba tun wa rọ lawọn ọna naa kii ṣe kekere.
- Ẹ dákun ẹ ran Iyabo Oko lọ́wọ́, ìyá ti ń ṣàárẹ̀ láti ọdún márùn ún sẹ́yìn, o ti kọjá agbára wa- Foluke Daramola Salako
- Ṣọ́ọ̀ṣì wó pa èèyàn méjì ní Taraba, àwọn míràn farapa
- Lébìrà tó jí iriniṣẹ́ iná mọ̀nàmọ́ná a fi ẹgba àtòrì méjìlá ṣara rindin kó lè kọ́ ẹ̀kọ́
- Okòòwò márùn ún tí o lè bẹ̀rẹ̀ nínú ilé rẹ̀
- Wo iye kọ́ńdọ́mù táwọn ọmọ Nàìjíríà fi ń ṣara rindin lọ́dún












