Oyo local government election: Ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo ti fòfin de lílọ àti bíbọ̀ ọkọ̀ láti aago mẹ́fà sí mẹ́ta ọ̀sán nítorí ìdìbò ọ̀la

Ajọ eleto idibo ipinlẹ Ọyọ ti fun awọn alaga ijọba ibilẹ mejilelọgbọn to jawe olubori ni iwe eri iyanisipo.
L'ọjọ Aje ni alaga ajọ eleto idibo ipinlẹ Ọyọ, Aarẹ Isiaka Ọlagunju fi iwe ẹri iyanisipo le awọn alaga ijọba ibilẹ mejilelọgbọn ti awọn ara ilu dibo yan lọwọ.

Ninu ọrọ ti o sọ lẹyin ti o fun wọn ni iwe ẹri naa, Ọlagunju parọwa si awọn alaga tuntun lati ma ja awọn eeyan ilu to fun wọn ni anfani iyansipo kulẹ.
O kesi wọn lati riidaju wi pe wọn mu awọn ileri ti wọn ṣe lasiko ipolongo ibo ṣẹ.
- Auxiliary àtàwọn míì gba ìwé ìyànsípò tuntun gẹ́gẹ́ bí ìjọba ìbílẹ̀ ṣe gba ìṣàkóso àwọn ibùdókọ̀ nípinlẹ̀ Oyo
- Àìṣàtìpó rí ló ń da Ejiogbe láàmú, àsìkò ìjọba tèmi ló dé- Alhaji Mukaila Auxilliary
- Ìdí rèé tí mo fi yan ikọ̀ PMS rọ́pò NURTW nípìnlẹ̀ Oyo - Seyi Makinde
- APC ni Auxilliary ṣiṣẹ́ fún lásìkò ìdìbò gómìnà 2019 kìí ṣe PDP-Oyo NURTW
- Auxiliary korò ojú sí àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ tó ń dàlú rú
Lara awọn alaga ajọ eleto idibo fun ni iwe ẹri ni: Arakunrin Raheem Akeem Adepoju (Oorelope), Sulaiman Adediran (Irepo), Arabinrin Juliana Oluwakemi Akanni (Olorunsogo), Akanji Kabir Ayoade (Ogbomoso North), Oyeniyi Timothy Oyedokun (Ogbomoso South), Olugbenga Obalowo (Ibarapa East).
Jelili Oyinloye Adebare (Iwajowa), Fasasi Adeagbo (ATISBO), Arabinrin Ramat Adeniran (Saki-East), Sarafadeen Omirinde (Saki-West), Adebare Muraina Afolabi (Kajola), Adesoye Seun Ojo (Ogo-Oluwa) ati Bolaji Ojo Akintola (Itesiwaju).

Awọn omii ni; Olateju Michael Alabi (Oriire), Adegbite Isaiah Alabi (Surulere), Adedoyin Oloyede Adeoye (Ibarapa Central), Lateef Adebayo Lawal (Ibarapa North), Muftau Osuolale (Iseyin) ati Sunday Akindele Ojo (Afijio).
Ajọ naa ti kede rẹ wi pe atundi ibo yoo waye ni ijọba ibilẹ Ido l'Ọjọru.
Ayipada naa waye nitori aikopa ẹgbẹ oṣelu ZLP nibi eto idibo ọjọ Abamẹta nipasẹ iyọkuro ami idanimọ ẹgbẹ oṣelu naa ninu iwe idibo.

Ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo fòfin de lílọ àti bíbọ̀ ọkọ̀ láti aago mẹ́fà sí mẹ́ta ọ̀sán nítorí ìdìbò ọ̀la

Oríṣun àwòrán, @Makinde
Ijọba ipinlẹ Ọyọ ti fi ofin de lilọbibọ laarin aago mẹfa owurọ si mẹta ọsan nitori eto idibo ọjọ Satide
Ijọba ipinlẹ Ọyọ ti kede rẹ wi pe ko ni si anfani fun lilọbibọ awọn eeyan ati igbokegbodo ọkọ laarin aago mẹfa owurọ si mẹta ọsan ọjọ Abamẹta.
Atẹjade ti wọn fi lede lati ọwọ akọwe ijọba ipinlẹ Ọyọ, Arabinrin Olubamiwo Adeosun kede rẹ.
- Kí ni IMEI ara fóònù àtí ìwúlò rẹ̀, tí ìjọba fi ń béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ aráàlú?
- Ajimobi kò ṣe NYSC tó fi di gómìnà, àmọ́ wọ́n yọ mí ní Mínísítà torí ẹ̀ṣùn yìí - Adebayo Shittu
- Ẹ wo ọ̀nà mẹ́jọ tí ìkọlù Israel fi ṣe àkóbá ńlá lórí ìgbé ayé aráàlú Gaza
- N kò tako Yoruba Nation, ohun tí mo sọ nípa Sunday Igboho rèé - Aseyin
- Àwọn olórí ìjọ méjì ni wọn jí gbé ní ìjọ àgùdà ní Katsina- Rev Fr Chris
- Ìwádìí rèé lórí gbas-gbos tó wáyé lórí ikú ọmọogun òfúrufú l'Oshodi l‘Ọ́jọ́bọ
- Alimotu Pelewura, Ìyálọ́jà akọ́kọ́ l’Eko tó mi amúnisìn àti ìjọba tìtì
Akowe ijoba ipinle Oyo ni wi pe ofin ti wọn fi de lilọbibọ pọn dandan ki awọn oludibo ni ijọba ibilẹ mẹtalelọgbọn to n bẹ ni ipinlẹ Ọyọ le ṣe ojuṣe wọn ni irorun ninu eto idibo ti yoo waye lọjọ kejilelogun oṣu kaarun ọdun yii.
Atẹjade naa tọka rẹ wi pe lilọbibọ awọn eeyan ati ọkọ akẹru ko ni waye laarin aago mẹfa owurọ si mẹta ọsan ki awọn oṣiṣẹ ajọ eleto idibo ipinlẹ Ọyọ naa le ṣiṣẹ wọn lai si idiwo tabi idena.
Ajọ naa kesi gbogbo awọn oludibo to ti fi orukọ silẹ lati kopa ninu ibo naa ki wọn si tẹlẹ ofin ijọba, pẹlu afikun wi pe awọn eeyan to fẹ nnkan pataki ti ofin ti lẹyin nikan ni yoo laarin lati rin soke-sodo ni asiko yii.

Oríṣun àwòrán, @others















