Oshodi Military Crisis: Kí ni ìdí abájọ wàhálà lórí ikú ọmọogun òfúrufú l'Oshodi?

Oríṣun àwòrán, other
Ọpọlọpọ awọn olugbe Oshodi nipinlẹ Eko atawọn to n wọ ọkọ nibẹ ni wọn sa asala fun ẹmi wọn lọjọbọ, lori wahala to bẹ silẹ laarin awọn ọmọogun kan atawọn janduku lagbegbe naa.
Agbegbe Mosafẹjọ ni Oshodi ni iṣẹlẹ naa ti waye.
Gẹgẹ bi awọn iroyin abẹle kan ṣe sọ, awọn ologun naa ya bo Oshodi "lati gbẹsan iku ọmọogun ofurufu kan, ti awọn janduku pa lagbegbe naa"
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ṣé lóòtọ́ ni mọ́tò tó kọ́wọ̀rín pẹ̀lú Seyi Makinde pa ọmọdébìnrin kan l'Ogbomoso?
- Alimotu Pelewura, Ìyalọ́ja akọ̀kọ̀ l’Eko tó mi amúnisìn àti ìjọba tìtì
- Ó yẹ kí Aàrẹ Buhari yọ Malami nípò lórí ọ̀rọ̀ tó sọ nípa ẹ̀yà Igbo àti àwọn darandaran- Amofin Adeoye
- Ìdí rèé tí mo fí kọ PDP sílẹ, lọ darapọ̀ mọ́ APC- Ben Ayade
- Ọlọ́pàá ní ká san ₦500,000 fún béèlì baba Ijesha, mo yarí torí ọ̀fẹ́ ni béèlì - Amòfin Ogunlana
Ọpọlọpọ ọkọ ero ni wọn bajẹ tawọn awakọ ero si sa fi skọ silẹ, bẹẹ lawọn ọlọja pẹlu juba ehoro ti wọn si fi ṣọọbu wọn silẹ.
Awọn miran sọ pe wọn ri oku ọmọogun naa ni agbegbe naa ti awọn eeyan si fura pe awọn janduku lo gba ẹmi rẹ ki wsn to fi awọn ṣọja naa ṣọwọ sibẹ lati lọ gbe oku rẹ ki wọn si le awọn janduku kuro lagbegbe naa.
Amọṣa ileeṣẹ ọlọpaa ti fi atẹjade kan sita pe awọn ti bẹrẹ si ni wadi ohun gan to fa wahala naa.
Alukoro ileeṣẹ ọlọpaa ni ipinlẹ Eko, Muyiwa Adejọbi ṣalaye ninu atẹjade naa pe, " Ileeṣẹ ọlọpaa ni ipinlẹ Eko gbọ si wahala to waye lagbegbe Capa Park/Mosafẹjọ ni Oshodi loni Ọjọbọ ogunjọ oṣu karun un ọdun 2021 ni agogo meje owurọ. A ti da alaafia pada si agbegbe naa, a si n ṣe iwadii lori rẹ.
A rọ awọn olugbe ilu Eko lati maa ba iṣẹ wọn ls laisi wahala."













