Ọkùnrin kan dèrò ẹ̀wọ̀n lẹ́yìn tó jí súùtì àti àwọ̀tẹ́lẹ̀ ọkùnrin nílé ìtàjà ìgbàlódé Abuja

Oríṣun àwòrán, others
Ọkùnrin kan rí ẹ̀wọ̀n he lẹ́yìn tó jí súwìtì àti àwọ̀tẹ́lẹ̀ ọkùnrin l'Abuja,
Ọkunrin ẹni ogoji ọdun kan ti ri ẹwọn ogoji ọjọ he lẹyin ti ile ẹjọ kan niluu Abuja sọ pe o jẹbi jiji suwiti ati awọtẹlẹ ọkunrin nile itaja igbalode kan.
Adajọ naa, Inuwa Maiwada ṣedajọ ọhun lẹyin ti Kabiru Zakari ni oun gba pe lootọ ni oun jẹbi ẹsun ti wọn fi ka noun.
Ṣugbọn Adajọ naa fikun pe Zakari le san owo itanran ẹgbẹrun mẹwaa naira dipo ko lọ fi ẹwọn jura, ko si tun ṣeleri pe oun ko ni ṣe bẹẹ mọ.
- Kílódé tí Ọọni Ife, Oba Ogunwusi kò fi gbọdọ̀ rí ọmọ rẹ̀ tuntun ti Olorì Naomi bí títí di bíi ẹ̀yìn oṣù mẹ́fà?
- Ìbálòpọ̀ ọ̀lọ́jọ́ méje mú kí ilé ẹjọ́ tú ìgbéyàwó ọdún mẹ́wàá ká ní Ibadan
- Fatai Rolling Dollar, Ọmọ ìdílé oyè tó gbé igbá orin tí Ebenezer Obey ń ṣiṣẹ́ lábẹ́ rẹ̀!
- Kí lo mọ̀ nípa ìbẹta kan ṣoṣo tí Alaafin Oyo bí? Wọ́n pé ọdún méjìlá báyìí
Adajọ ọhun tun pa lasẹ ki ọdaran naa lọ kẹkọọ nipa imọ Islam lasiko to ba n sẹwọn lọwọ ki ayipada le de ba aye rẹ.
Olupẹjọ, Ayotunde Adeyanju ni ọkunrin kan, Agida Stephen, to jẹ oludari ile itaja igbalode Fordmart to wa lagbegbe Karu, ni Abuja lo fẹsun kan Zakari pe o jale ninu ile itaja oun.
O ni Zakaru dibọn bi onibara, o wọ ile itaja naa o si ji igo omi, suwiti, ati awọtẹlẹ ọkunrin ti iye owo rẹ to ₦4,500.
- Ọ̀rọ̀ àsọkẹ́yìn Diego Maradona ìlúmọọká agbábọ́ọ̀lù rèé kó tó dágbére f'áyé
- Omotara kan ìdin nínú iyọ̀, àwọn ọmọ ilẹ̀ Faranse náà bínú síi nítorí alágbe tó fi ṣe yẹ̀yẹ́.
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá palẹ̀ òkú ọmọ ọjọ́ kan mọ́ lẹ́yìn t́i wọ́n jùú sórí ààtàn
- Àwọn Olúkọ ìpínlẹ̀ Oyo fakọyọ lórí ètò Akọ́mọlédè àti Àṣà púpọ̀
Oludari ile itaja naa ṣalaye pe Zakari ko awọn ohun to ji ọhun pamọ sabẹ awọtẹlẹ re, to si san owo igo omi nikan.
Ṣugbọn ọdaran naa ko mọ pe ẹrọ CCTV ile itaja naa ti ka gbogbo ohun to ṣe silẹ.
Olupẹjọ naa sọ pe iwa ti Zakari wu yii lodi si ofin iwa ọdaran ti ẹsẹ 348 ati 288 ti orilẹ-ede Naijiria, o si yẹ ki ile ẹjọ fi iya to tọ jẹ ẹ.
- Kí lo mọ̀ nípa ìbẹta kan ṣoṣo tí Alaafin Oyo bí? Wọ́n pé ọdún méjìlá báyìí
- Ọmọbìnrin tó tayọ nínú ìdànwó WAEC ọdún 2019 pẹ̀lú A1 méje ti kú
- Nàìjíríà fohùn ránṣẹ́ padà sílé aṣofin UK pé ọ̀rọ̀ EndSars kò sí lẹ́nú wọn láìgbọ́ ìwádìí tán!
- Orúkọ Aisha Yesufu náà wọ inú BBC 100 Women tí a fi ń sọri àwọn obìnrin tó pegedé ní 2020

















