EKSU: Bukola gún Jọ́ọ́nù ọ̀rẹ́kúnrin rẹ̀ pa ní Fásitì ìpínlẹ̀ Èkìtì nítorí àìrówó irun san

Oríṣun àwòrán, @ArtsMalo
Ọmọ ileewe Fasiti ipinlẹ Ekiti kan, Bukola Odeyemi, ti gun ololufẹ rẹ pa.
Ọmọ ogun ọdun naa, lo gun ololufẹ rẹ, John Iju, to jẹ ọmọ ọdun mejilelogun pa, nitori o kuna lati fun un ni ẹgbẹrun meji abọ naira lati fi se irun.
Iroyin sọ wi pe, ọrọ naa ṣẹlẹ ni Iworoko-Ekiti, ni agbegbe ibi ti awọn ọmọ ileewe naa n gbe, ni nkan bi aago mẹwa aṣalẹ.
- Kemi Olunloyo ń làjà láàrin Toyin àti Lizzy lọ́wọ́
- Lizzy Anjorin: Mi ò bẹ Toyin o! Ẹ̀yin olólùfẹ́ mi àti ẹbí ni mo bẹ̀
- Ọlọ́pàá kò rí ǹkankan lábẹ́ pẹpẹ ilé ìjọsìn mi - Olùṣọ́àgùntàn Akure
- Ọmọ Naijiria tó lé ní 300 ti padà wálé láti South Africa
- Àwọn olólùfẹ̀ Toyin Abraham ati Liz Anjorin ti gbé ọ̀rọ̀ wọn rù sórí, ẹ wo òjò òkò ọ̀rọ̀
Ikuna John lati fun Bukọla ni owo irun yii lo da ija nla silẹ laarin wọn, sugbọn ni igba ti ọwọ ologbe ọhun le ju ti Bukọlalọ, lo mu ọbẹ, to si gun ni igba aya.
Awọn oṣoju mi koro ni agbegbe ile igbe awọn awọn ọmọ ileewe naa salaye fun awọn oniroyin pe, lẹyin ti Bukola gun ọrekunrin rẹ yii ni o n da ẹjẹ lara, to si jẹ Ọlọrun nipe loju kan naa.
Awọn ọrẹ oloogbe yii lo fi ọrọ naa to ajọ ọlọpaa leti.
Alukoro awọn ọlọpaa ni ipinlẹ Ekiti, Caleb Ikechukwu, fi idi ọrọ naa mulẹ, to si sọ wi pe ọwọ ofin ti tẹ afurasi naa, ti iwaadi si ti n lọ lọwọ.









