EU: Òfo ni ètò ìdìbò 2019 ní Naijiria

EU EOM

Oríṣun àwòrán, Google

Àkọlé àwòrán, Ẹka to n se iwadii ni Ajọ Isọkan Yuroopu, EU EOM ni awọn ri asemase ninu eto idibo to kọja lorilẹede Naijiria.

Ọpọlọpọ awuyewuye lo ti jẹyọ lori atẹjade ti Ajọ Ilẹ Yuroopu(European Union) fi lede nipa idibo ọdun 2019.

Ẹka to n se iwadii ni Ajọ Isọkan Yuroopu, EU EOM ni ofo ni idibo sipo aarẹ, ti ipo gomina ati si ile igbimọ asofin apapọ lorilẹede Naijiria.

Àkọlé fídíò, Éégún tó wà nídí Yoruba Bollywood, Samo Baba f'ojú hàn o!

Igbakeji Adari ẹka naa, Hannah roberts lo sọ bẹẹ lasiko to n ba awọn oniroyin jomitoro-ọrọ ni Abuja, olu ilu Naijiria.

Wọn jẹ ko di mimọ pe bi o tilẹ jẹ wi pe ajọ eleto idibo, INEC sọ pe iroyin naa waye ni irọwọ ohun irọsẹ.

Àkọlé fídíò, Olusegun Obasanjo: Ọmú ìyá mi ti mo fi ń mùkọ ni kekere ló jẹ ki ń lókun

Ṣugbọn iwadi ẹka ajọ EU naa fi han pe awọn kudiẹ kudiẹ ṣi wa ninu ilana eto idibo naa.

EU EOM

Oríṣun àwòrán, Google

Amọ, Ajọ EU ni awọn ko mọ nkankan nipa ẹrọ ‘server’ ti ẹgbẹ oselu PDP sọ wi pe Ajọ INEC fi ko esi idibo jọ lasiko idibo gbogboogbo to waye.

Àkọlé fídíò, Alapinni Oosa ṣàdúrà fún gogbo ọmọ kúoótù, oò jíire bí?