Àkọlé àwòrán, Àwọn ọmọ Nàìjíríà ń sáré wọ inú ọkọ̀
Ọpọlọpọ ọmọ Naijiria to le ni igba ẹgbẹrun lo ti ya soju opo Twitter wọn lati ọjọ abamẹta ti ajọ INEC sun ọjọ idibo Naijiria siwaju ti wọn si n ke tantan pe orilẹede Canada lo ku ti awọn yoo mori le.
Eyi wa lara ọna ti awọn ọmọ Naijiria n gba fi ẹhonu han lẹyin ti wọn ji lowurọ kutu hai lati lọ dibo ti wọn wa ṣaa dede gbọ pe ajọ eleto idibo ti sun idibo siwaju lọjọ idibo gangan iyẹn lati ọjọ kẹrindinlogun oṣu keji lọ si ọjọ kẹtalelogun oṣu keji ọdun 2019.
Awọn ọmọ Naijiria ọhun to n fi ibinu wọn han n sọ pe, niwọn igba ti ajọ INEC ti jawọn kulẹ, awọn yoo fi Naijiria silẹ lọ si Canada.
Amọ ṣaa, yẹyẹ ni ọpọ fi ọrọ naa ṣe.
Nitori naa, latari ariwo "Canada ya" t ogbode kan, ẹ wo alaye kikun nipa iye akoko ti yoo naa ẹni to ba fẹ rawọle irinajo yii nipa ibeere ati idahun to wa nisalẹ.
O fẹ ẹ kuro l'orilẹede Naijiria, iye asiko wo ni yoo gba ọ?