Niyi Akinsiju: Ìjọba gbọdọ̀ wá nkàn ṣe sí i

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ija to n ṣẹlẹ loorekoore laarin awọn ọlọpaa ati awọn ajọ eleto abo miiran bi ologun ati àjọ àbò ara ẹni làbò ìlú tumọ si pe nkan o fara rọ pẹlu eto aabo orilẹede Naijiria.
Eyi ero ẹnikan to jẹ onwoye ohun to n lọ lawujọ nigbati o ba ile iṣẹ wa BBC Yoruba sọrọ lori fidio kan to fihan bi ọlọpaa kan ti gbiyanju lati fipa gba ibọn lọwọ oṣiṣẹ àjọ àbò ara ẹni làbò ìlú kan.
Ohun tó fi yé wa ni pé àwọn ọlọ́pàá àti àwọn àjọ elétò ààbò yókù ní orílẹ́èdè Nàìjírìa nílò ẹ̀kọ́ sii lórí ìbọn gbígbé àti ìbáṣepọ̀ tó wà láàrin àwọn òṣìṣé elétò ààbò.










