Sunday Igboho: Deji Adeyanju bu ẹnu àtẹ́ lú ìkọlù DSS sílé Igboho

Oríṣun àwòrán, DSS
Ajàfẹ́tọ ọmọniyan, Deji Adeyanju ti woye pé kò le jẹ́ Sunday Igboho lo ni awọn ibọn ti DSS bá nílé rẹ̀.
Deji Adeyanju fìdí ọ̀rọ̀ yìí múlẹ̀ lójú òpó ìkànsíraẹni ayelujara rẹ̀, to sì bẹnú àtẹ́ lu bi àwọn osisẹ agbofinro ṣe ṣekúpa àwọn ènìyàn méjì nílé Igboho.
Bákan náà ló ní ó yẹ kí Igboho maa dúpẹ́ lọ́wọ́ ẹlẹ́dàá rẹ̀ pé ìbọ̀n ni wọn dẹ sílẹ̀ nílé rẹ̀, kìí ṣe àdó olóró.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Kí ló dé tí DSS kó bàńtẹ́ òògùn, ba ilé Sunday Igboho jẹ́ lái fara pa?
- "DSS, níbo ni ₦2m àti owó Euro, Dollar àti Pound Sterling tẹ kó nílé mi wà? "
- Sunday Igboho, ìsáǹsá rẹ̀ kò lé sá mọ́ wa lọ́wọ́, mímú lá mú ọ - DSS fọwọ́ gbáyà
- Sunday Igboho ń ṣọ̀fọ̀ ọ̀kan lára àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ tí DSS pa
- À ṣe ìwọ́de Yoruba Nation l‘Eko, bí ọlọ́pàá fẹ́, bó kọ̀ - Igun Sunday Igboho
- "Sunday Igboho, Banji Akitoye, ẹ rìn jìnnà sójú pópó Eko fún ìwọ́de Yoruba Nation"
- Afenifere figbe bọnu pé ìkọlù sí òmìnira àti ẹ̀tọ́ láti sọ̀rọ̀ ti padà dé
- Ìbọn àti nǹkan ìjagun ni Igboho kó pamọ sílé ló jẹ kí á yabo ilé rẹ̀ - DSS
- Gani Adams tutọ́ sókè fójú gbà lórí ìkọlu sílé Sunday Igboho
- Níbo ní Sunday Igboho wà lẹ́yìn ìkọlù síle rẹ̀? Ọ̀pọ̀ ọmọ Nàíjíríà ń bèèrè
"Ó yẹ́ kí Igboho máa dúpẹ́ lọ́wọ́ ẹlẹ́dàá rẹ pé ìbọn ni wọ́n gbé wa sílé rẹ̀, kìí ṣe adó olóró"
"Wọn pa ènìyàn méjì nílé Igboho, wọ́n sì ń se bi ẹ ni pé wọ́n kò tilẹ hùwà ọ̀daràn kankan.
Sáájú ni ilé iṣẹ́ ọ̀tẹlẹmúyẹ ti sọ pé àwọn ni àwọn lọ sí ilé Sunday Igboho, lẹyin ti wọn ta àwọn kan ta awọn ni olobó pé Sunday Adeyemọ kó nǹkan ìja ogun pamọ sílé.
Bákan náà ni wọ́n fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé àwọn pa àwọn ènìyàn méjì nínú àwọn tó dójú ìjà kọ àwọn
Adeyanju ni kò sí ẹni tí ó kọjá òfin pe, ìgbàgbọ́ sì wà pé, àwọn tó kù tí wọ́n kó nílé Sunday Igboho yoo lọ fojú ba ilé ẹjọ́.
Àwọn nǹkan ti wọ́n kéde pé àwọn bá ní ilé Sunday Igboho ni, oníruuru Ibọn, ìwé ìrìna lóríṣirísi, owó dọ́là àti àwọn nǹkan mííràn bi ọkọ̀.

















