Oba Sunday Oladapo: Ṣé lóòtọ́ ni wọ́n rọ Oba Ijeru, Onpetu Sunday Oladapo lóyè?

Oríṣun àwòrán, Oba Sunday Oladapo
Onpetu ti Ijeru nipinlẹ Oyo, Oba Sunday Oladapo ti rọ awọn ọmọ ilu naa lati gboju kuro nibi iroyin kan to sọ pe wọn ti rọ oun loye.
Ilu Ijeru ko fi bẹẹ jina si Ogbomoso,ni eyi to si jẹ pe abẹ Ogbomoso si ni ilu naa wa ni ipinlẹw Oyo to wa ni Iwo oorun guusu Naijiria.
Ninu atẹjade kan to fi sita, eyi to tẹ BBC lọwọ ni Oba Oladapo ti sọ pe ayederu ni iroyin to n lọ lori ayelujara pe wọn ti rọ oun loye.
Oba Oladapo sọ pe idajọ ile ẹjọ kan lo mu ki awọn eeyan kan ma a gbe iroyin ọhun.
O ni ṣugbọn, abala kan pere ninu idajọ ni wọn n fi sinu iroyin wọn.
- Mo ti ra ilẹ̀ ìsìnkú mi ní 'Ebony Vault' ṣùgbọ́n....
- Wo ǹkan mẹ́jọ tí o kò mọ́ nípa Olubadan, Oba Saliu Adetunji tó re ìwàlẹ̀ àṣà..
- Ṣé lóòtọ́ ni ìjọba àpapọ̀ fẹ́ pa Sunday Igboho sí ẹ̀wọ̀n? Agbẹjọ́rò rẹ̀ sọ̀rọ̀
- Aare Muhammadu Buhari ránṣẹ́ sí ìlú Ogbomoso lórí ikú Soun
- Ilẹ̀ ń j'ẹ̀nìyàn! Ka nípa àwọn Ìlúmọ̀ọ́ka tó dágbére fáyé ní 2021
O ni ko si ẹjọ kankan lori iyansipo oun gẹgẹ bi ọba.
"Idajọ ile ẹjọ ti awọn ileeṣẹ iroyin kan fi gbe iroyin wọn jade, lo da lori ede aiyede to waye larin Oba Yesufu Abidoye Mobolade ati Oloye Adeleke Lawal, ati awọn meji miran.
Ti wọn si gbe ara wọn lọ si ile ẹjọ giga to wa nilu Ogbomoso.
"Koda, ile ẹjọ kotẹmilọrun ti Oba Mobolade pada gbe ẹjọ lọ nilu Ibadan sọ lọdun 1999 pe ọrọ oye ilu ni ọrọ naa, ti ko si dasi. "
Oba Oladapo ni awọn meji ti ọrọ naa kan ti ku ṣaaju idajọ ile ẹjọ kotẹmilọrun, ati pe nkan ti wọn n ja si ko ni ohunkohun lati ṣe pẹlu ipo ọba Onpetu ti ilu Ijeru.
- 'Àṣírí ọkọ mi tú sími lọ́wọ́, ṣé mo le dáríjì í?'
- Wo bí àwọn gbajúmọ̀ tí ẹ̀ fẹ́ràn yìí ṣe tẹ̀ẹ́ wọ́nú ọdún 2022 àtí ohun t'Ọ́lọ́hun gbé wọn borí
- Àsọtẹ́lẹ̀ 2022 àti ìgbésẹ̀ tí Pásítọ̀ Enoch Adeboye fẹ́ gbé lórí ìdojúkọ Nàìjíríà nìyí
- Ohun tí CAN fi ṣíde ọdún 2022 fún gbogbo ọmọ Nàìjíríà nìyí
- Australia, New Zealand, Japan,àwọn orílẹ̀-èdè tó ti ṣáájú Nàìjíríà wọ ọdún 2022














