Namibia Himba Women: Èéfín iná àti amọ̀ ni àwọn obìnrin yìí fi n ṣe ara lóge

Ara ọtọ ni awọn eniyan ẹ̀yà Himba lorilẹ-ede Namibia, nitori àṣà ati ìṣe wọn to yatọ si ti gbogbo aye.
Ẹya yii jẹ gbajugbaja ni Namibia, ti wọn si ma n pe wọn ni 'red people', eyi to tumọ si awọn eniyan pupa.
Awọn eeyan ẹ̀yà yii to ẹgbẹrun lọna aadọta, bẹ́ẹ̀ si ni awọn kan gbagbọ pe awọn obinrin wọn lo rẹwà julọ ni Africa.
Bo tilẹ jẹ pe awọn obinrin naa kii wẹ, ti wọn kii si fi omi ṣan ọwọ wọn, sibẹ wọn ko burẹwa.
- Wo ilúbìnrin tí wọn ti ń ní ìbálòpọ̀, bímọ̀ láì ní ọkọ
- Àìrìjìnà ni àìrábuké ọ̀kẹ́rẹ́, orí ọ̀kadà ni wọ́n ń gbé òku sí lọ mọ́súárì
- Èèmọ̀ rèé o, Dókítà yọ eyín 526 lẹ́nu ọmọ ọdún méje
- Bí òkú ṣe máa ń bàjẹ́ ní Mọ́ṣúárì tẹ́ẹ ò bá san owó ìtọ́jú fáwọn olùtọ́jú òkú rèé
- Wòlíì tó ní kí wọ́n sin òun láàyè torí agbára ìṣẹ́gun, gba ibẹ̀ sọdá sí ọ̀run
- Èèmọ̀! Àrùn tuntun Marburg, tó le ju Covid-19 lọ gbòde lágbàáyé
Ọna wo ni wọn n gba ṣe itọju ara wọn, ti wọn o fi ki n run?
Nise ni àwọn obinrin naa ma n fi èéfín ina wẹ lati le tun ara ṣe. Bii ti báwo?
Lojoojumọ, awọn obinrin naa ma n ko eedu to ni ina lara sinu ikoko, wọn o si da oriṣiriṣi ewe ati egbo igi sinu rẹ.
Ti eefin ba ti n rú, wọn yoo tẹ ara wọn ba sori ikoko naa. Eefin to ba n jade yoo mu ki wọn o laagun, ti o n fọ ara wọn.
Lati wẹ gbogbo ara, wọn o fi aṣọ nla bo ara wọn, ki eefin ba a le duro si ara rẹ fun oogun.
Yatọ si eyi, ẹẹmeji ni wọn ma n fi ori ati amọ pupa pa ara wọn nitori oorun ati kokoro.
Awọn eniyan Himba gbagbọ pe àwọ̀ pupa jẹ àpẹẹrẹ ilẹ ati ẹ̀jẹ̀.
Aṣọ penpe ti wọn fi awọ ewurẹ ṣe ni awọn obinrin yii ma n wọ, ti wọn si ma n fi amọ pupa kun irun ori wọn.
Idi ti awọn eniyan naa kii se fi omi wẹ nipe, oju ọjọ lágbára pupọ lagbegbe wọn.

Inu aginju ni wọn n gbe, eyi to mu ko nira lati ri omi lo.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- PDP ni yóò mú ọmọ Nàíjíríà kúrò lóko ìyà tí wọn wà ní 2023 - Kola Ologbondiyan
- Wòlíì tó ní kí wọ́n sin òun láàyè torí agbára ìṣẹ́gun, gba ibẹ̀ sọdá sí ọ̀run
- Ọmọ ìyá méjì tó ń lọ ṣe ìdánwò NECO wà lára èèyàn márùn ún tí tírélà agbépo tẹ̀ pa n'Ibadan
- Ilé ẹjọ́ pàṣẹ kí wọ́n ó fi Chidinma Ojukwu tí wọ́n lo pa Ataga sí ẹ̀wọ̀n
- Ajínigbé yìnbọn pa ọkọ, jí ìyàwó àti ọmọbìnrin rẹ̀ gbé lọ l'Ekiti
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ni ìbálòpọ̀ lásìkò nǹkan oṣù lè ṣekúpa ọkùnrin?
- Babaláwo fi ọ̀dọ́ tó fẹ́ ṣe òògùn owó, ṣe ètùtù owó fún ara rẹ̀
Ko tan sibẹ o. Àwọn obinrin yii tun ma n fi ibalopọ ọ̀fẹ́ ṣe alejo, ti ọpọ wọn si maa n fi ara silẹ lai wọ asọ to bo ọmu wọn.
Lojoojumọ si ni awọn eniyan ẹ̀yà yii n sisẹ karakara lati daabo bo àṣà wọn.

















