Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́

Àkọlé fọ́nrán ohùn, Àkójọpọ̀ ìròyìn káàkiri Nàìjíríà
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Njẹ o mọ pe o ti le lọsẹ kan bayii ti ko ti si ina ni Ariwa Naijiria?

Ki lo de? Wọn gbayawo awọn oṣiṣẹ apinnaka ni?

O maa kọja bẹẹ, ọpọ nnkan lo ti bajẹ nitori aisi ina, Koda, awọn oniṣowo ti n sọ pe bii kawọn filu silẹ lo ri .

Ileeṣẹ to n pinna, TCN, sọ fun BBC pe ai si ina ko ṣẹyin awọn oju opo meji to bajẹ ni Shiroro ati Kaduna

Aṣe loootọ ni pe oju ni maaluu n rọ, ọbẹ o daa lọrun

Ko sẹni to fẹ ẹ ku

Bẹẹ gan-lori fun Ramon Adedoyin, to gba ile ẹjọ kotẹmilọrun lọ nitori idajọ iku ti wọn da fun un lori iku Timothy Adegoke

Ẹkunrẹrẹ bi igbẹjọ naa ṣe waye wa ni bbc.com/yoruba

Ko sowo, ko siṣẹ

Se o ti gbagbe pe ẹni ti ko ba ṣiṣẹ, ko yẹ ko jẹun ni?

Awọn oṣiṣẹ fasiti lo ni awọn ko nii pada sẹnu iṣẹ titi ti ijọba yoo fi san owo to jẹ awọn

Ọjọ Aje ọsẹ yii ni wọn bẹrẹ iyanṣẹlodi, lori owo oṣu mẹrin tijọba jẹ wọn.

Lọ soju opo wa lati mọ bo ṣe n lọ

Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́