Bali: Imam kọ̀ láti dá ìrun dúró nínú ilẹ̀ ríri Bali

Oríṣun àwòrán, FACEBOOK/MUSHOLLA AS-SYUHADA BLK
Àwọn ọmọ orílè-èdè Indonesia ti n kán sára sí Imam kan tó kọ láti dá irun dúró nígbà tí ilẹ rírí ṣẹlẹ ní ìlú Bali.
Imam náà ẹní ti orúkọ rẹ n jẹ Arafat dúró gidigba tí kò sì dá irun dúró tóun tí bí àwọn janmọọ to n kirun lẹyìn rẹ kan ṣẹ f'ẹsẹ fẹẹ.
Agbẹnusọ kan fún mosalasi As-Syuhada sọ fún ilé iṣẹ BBC pé àwọn tó n kirun lẹyìn imamu náà lawọn ''sadede gbọ tí àjà bẹrẹ sí ní mí to sì dàbí wí pé ilé náà yóò yà lulẹ̀ làbá sá asalà fún ẹmi wa''
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post
Agbẹnusọ náà so wí pé Imam náà tẹẹ pá nítorí "Ọlọhun nìkan ló lè gb'ẹmi rẹ".
Ọkẹ àìmọye èèyàn lo ti ba ìṣẹlẹ ilé rírí náà tó waye ni erékùṣù Lombok lọ.








