Buhari sacks Emefiele: Ṣé lóòtọ́ ni Ààrẹ Buhari ti gbaṣẹ́ lọ́wọ́ gómìnà Báǹkì àpapọ̀ Nàìjíríà, Godwin Emefiele?

Aarẹ Buhari ati Godwin Emefiele, gomina Banki apapọ NAijiria

Oríṣun àwòrán, other

Iroyin ahesọ kan jade sigboro lowurọ Ọjọru pe aarẹ orilẹede Naijiria, Muhammadu Buhari ti gba iṣẹ lọwọ gomina Banki apapọ orilẹede naa, Ọgbẹni Godwin Emefiele.

Oniruuru iroyin lo si ti jade lẹyin rẹ bi awọn ọmọ Naijiria kan ṣe n kan sara ni awọn kan n woye pe igbesẹ naa ko tọna.

Godwin Emefiele bọ si agbami iroyin paapaa julọ lori ayelujara nigba ti iroyin gbe e pe oun naa fẹ dije ati pe awọn ẹgbẹ kan ti ko ara wọn jọ lati ra fọọmu idije fun un.

Gbogbo eeyan lo pariwo sita nigba naa pe o ku diẹ kaato.

Awọn eekan bii Oby Ezekwesili, Amofin agba Fẹmi Falana, SAN, ẹgbẹ oṣelu PDP atawọn ẹlẹgbẹjẹgbẹ ni wọn pariwo pe ko fi ipo silẹ to ba fẹ dije fun ipo kankan gẹgẹ bi ẹtọ rẹ gẹgẹbi ọmọ Naijiria labẹ ofin.

Lẹyin igba naa ni Emefiele gba ile ẹjọ lọ lati bere fun alaye lori boya oun lẹtọ tabi oun ko lẹtọ labẹ ofin lati dije fun ipo aarẹ Naijiria lai kọwe fi ipo silẹ gẹgẹ bi gomina banki apapọ Naijiria.

Àkọlé fídíò, Ayodeji Rotinwa ni ìròyìnn òfegè gbé àwòrán rẹ̀ síta pè dókítà tó ń pa àwọn Hausa mùsùlùmí

Ṣe lootọ ni Aarẹ gbe igbesẹ yii?

Gbogbo iroyin to n jade lati ileeṣẹ aarẹ orilẹede Naijiria ko fi idi iroyin yii mulẹ.

Eeyan kan to sunmọ ileeṣẹ aarẹ pẹkipẹki ṣalaye fun BBC pebi awọn eeyan ṣe ji gbọ iroyin naa loju opo Twitter ni pupọ awọn naa gbọ ọ ati pe irọ to jina si otitọ ni.

Lasiko ti a fi n ko iroyin yii jọ, ko tii si atẹjade kankan lati ileeṣẹ ijọba Naijiria to fi idi rẹ mulẹ pe Aarẹ Muhammadu Buhari ti yọ Emefiele nipo gẹgẹ bi gomina banki apapọ Naijiria.

Ki ni ofin sọ nipa yiyọ gomina BAnki apapọ NAijiria nipo?

Amọṣa bi eeyan ba wo ofin to de idasilẹ ati akoso banki apapọ Naijiria, ko si ọna ti aarẹ lee fi ṣa dede gba iṣẹ lọwọ gomina banki apapọ Naijiria.

Abala kọkanla iwe ofin Centra Bank Nigeria Act 2007' sọ ọ di mimọ pe ida meji ninu mẹta gbogbo awọn aṣofin agba Naijiria ni lati fọwọ si yiyọ gomina Banki apapọ Naijiria ki aarẹ to lee yọ ọ nipo.

Àkọlé fídíò, Oba Adedokun Abolarin ti Oke Ila: Ó ya ọ̀pọ̀ tó súnmọ́ mi lẹ́nu bí mo ṣe ń kọ́