Osun Killings: Àwọn agbébọn ṣekúpa alága APC ní ìpínlẹ̀ Osun, ọlọ́pàá bẹ̀rẹ̀ ìwádìí

Oríṣun àwòrán, Leadership
Inu ibanujẹ ni awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu All Progressives Congress APC wa ni ipinlẹ Ọsun lẹ́yìn ti iroyin iṣekupa eekan ẹgbẹ naa kan lati ọwọ awọn agbébọn gbode.
Eni táa n wí yí gẹgẹ bí iroyin to tẹ wa lọwọ ni alaga ẹgbẹ ni ijọba ibilẹ ìlà oòrùn Atakumosa, Gbenga Ogbara.
Iroyin sọ pé l'owurọ kutu ọjọ Aje yii ni awọn agbébọn lọ ka mọlé rẹ ni Igangan ti wọn sì d'ẹmi rẹ legbodo.
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ní pé Osinbajo dalẹ̀ Tinubu pẹ̀lú bó ṣe kéde láti du ipò ààrẹ?
- Èèmọ̀ wọ̀lú! Àwọn agbébọn pa ènìyàn 135 lọ́jọ́ kan ṣoṣo
- Mo fi Ọlọ́run bẹ̀ yín, ẹ má bú ọkọ mi mọ́ torí ìgbéyàwó wa tó túká - Yewande Adekoya
- Àwọn ọmọ Palestine kọlu ìbòjì Josẹfu ọmọ Jakọbu, wọ́n dáná sun-ún
- Kí ló dé tí ọkùnrin yìí fi dojúkọ Kìnìún ààyè?
- "Ẹ̀yin onítíátà, ẹ gbàdúrà fún Kemi Afolabi, Ọlọ́run nìkan ló mọ ibi tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò já sí"
- Oluwo ṣe àbẹ̀wò sí Aláàfin lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ mẹ́ta tó gbé ìyàwó tuntun
- Bí Sunday Igboho bá sọ èròǹgbà rẹ̀ nípa Yoruba Nation, inú gbogbo ọmọ Yorùbá yóò dùn - Banji Akintoye
- Mo gbìyànjú láti ṣẹ́yún àkọ́bí mi saájú ìgbeyàwó - Iyabo Ojo
- Àgùnbánirọ̀ ya fọ́tò Bàbá Onílù láti tà á, òjò owó rọ̀ fún bàbá
Alukoro ileesẹ ọlọpaa n'ipinlẹ Osun Yemisi Opalola fidi iṣẹlẹ yi múlẹ.
Gẹgẹ bo ṣe wí, o ni ileeṣẹ ọlọpaa n tẹsiwaju pẹlu iwadii ati pe ko ni pẹ tàwọn yoo fi mu awọn to wa nidi iṣẹlẹ aburu yi.
Opalola ni: "Nnkan bi ago mejila oru ni awọn agbébọn ṣekupa alága APC. Ileese ọlọpaa sí ti fi awọn agbofinro ranṣẹ sí agbegbe naa.
"Iwadii ti bẹrẹ, kò sí ní pẹ tí ọwọ yóò fi tẹ awọn to wa nidi iwa aburu yi. Wọn kò ní lọ laijiya"














