Dayo Kujore: Ọmọ olóògbé olórin Juju fi àidunnú rẹ̀ lẹ́yìn tó ní àwọn èèyàn kò kẹ́dùn pẹ̀lú ẹbí rẹ̀

Oríṣun àwòrán, Dayo Kujore
Ọtitọ ni ọrọ tawọn Yoruba maa n sọ pe ọjọ ti a ba ku laa dere, eniyan o sunwọn laaye.
Ayinke Dayo Kujore to jẹ ọmọbinrin gbajugbaja olorin Juju to di oloogbe, Dayo Kujore lo pariwo sita pe awọn ọmọ Naijiria ko nan an ni rara lati ba ẹbi oloogbe kẹdun.
Ayinke fi ẹdun ọkan rẹ han loju opo Facebook rẹ nibi ti sọ pe awọn kii mọ iyi eeyan to jẹ ti wọn.
- Dayo Kujore: Àgbà olórin juju dágbére fáyé pé ó dìgbòóṣe!
- Àgbà olórin, Victor Olaiya jáde láyé.
- Wo ibi tí ọ̀rọ̀ Nnamdi Kanu dé dúró nílé ẹjọ́ lónìí
- Ibà Lassa tún ti ń sọṣẹ́ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà
- Wo àwọn ọmọ Yorùbá mẹ́fà tí ẹnu ń kùn lórí ìbò ààrẹ ọdún 2023
- Ọkùnrin kan gún ìyàwó rẹ̀ ọlọ́mọ mẹ́jọ pa nítorí pé ó ń ti ilẹ̀kùn mọ́rí
- Pásítọ̀ ti ríran sí mi pé mà á jẹ Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láti ọdún 2018- Dele Momodu
''O ṣeni laanu, o si buru jai bi awọn ọmọ Naijiria kii tii ka ohun to ba jẹ ti wọn kun.
Lẹyin ti Dayo Kujore lo gbogbo ọjọ rẹ lati sin orilẹede Naijiria ati ipinlẹ rẹ, Ogun, ko si ẹni to wẹyin lati ba ẹbi rẹ kẹdun.
Dayo Kujore lo ẹbun orin ti Eledua fi jinki rẹ lati ṣe igbelarugẹ aṣa orilẹede Naijiria.
Bakan naa ni o lo ẹbun rẹ lati so Naijiria pọ, ṣugbọn lẹyin ti o ti ku tan, ko si ẹnikan to kọwe ranṣẹ tabi wa lati bawa kẹdun.
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post
Eleyii buru jai! Ma a sun laya Olugbala baba mi, Wonder Dayo Kujore.
Ti eeyan ba maa n tun aye wa, mo ṣi maa tun jẹ ọmọbinrin rẹ.
Iku baba mi bami lojiji, mi o tiẹ lero rẹ rara, baba mi ọwọ, Idowu Adedayo Kujore, sun re o,'' Ayinke Dayo Kujore lo sọ bẹẹ.
Dayo Kujore gbajugbaja olorin Juju ni Naijiria ti dagbere faye lẹni ọdun mẹtalelọgọta.
Ọmọ bibi ilu Abeokuta ni Dayo Kujore ti ọpọ si mọ nitori ẹbun ti Eledua fun nipa arokọ ati agbekalẹ orin.
Oludasilẹ orin Sọkọ, Kujore kọṣẹ orin labẹ Prince Adekunle to si n ta gita ninu awọn orin manigbagbe ti Adekunle kọ bi "Aditu ede" ati "Eda n reti eleya".
- Bí EFCC ṣe mú ayédèrú ọ̀gágun sọ́jà Bolarinwa tó tún ní ẹ̀sùn jìbìtì owó N270m
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ èèyàn mẹ́rin tó ń jẹ́ ẹran ara èèyàn tí wọ́n tún ń tà ẹ̀yà ara èèyàn
- Àjọ NDLEA tanná wòdí Cubana
- Wo bí wọ́n ṣe gbẹ̀bí ọmọ tuntun yìí lójú òfurufú
- A ti fọwọ́ sí Lekan Balogun gẹ́gẹ́ bí Olubadan tuntun, kò sí wàhálà mọ́ - Ladoja
- Ọba Lamidi Adeyẹmi, òṣìṣẹ́ adójútòfò àti Abẹ̀ṣẹ́kùbíòjò kó tó jọba















