Ilé ẹjọ́ da ẹjọ́ tí Uche Secondus pè láti dá ìpàdé gbogbogbò ẹgbẹ́ PDP dúró nú

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ile ẹjọ kotẹmilọrun kan niluu Port Harcour ti dajọ pe ipade gbogbogbo ẹgbẹ oṣelu PDP gbọdọ tẹsiwaju lọjọ Satide gẹgẹ bi wọn ṣe gbero rẹ tẹlẹ.
Adajọ G.O. Kolawole to dari igbimọ ile ẹjọ naa da ẹjọ ti alaga ẹgbẹ oṣelu PDP tẹlẹ, Uche Secondu, pe lati wọgi le ipade naa nu.
Ṣugbọn ile ẹjọ ọhun sọ pe ẹjọ keji ti Secondus pe lori bi wọn ṣe yọ ọ kuro nipo alaga ẹgbẹ naa yoo tẹsiwaju.
- Ọ̀rọ̀ bẹ́yìn yọ lórí oyè ẹ̀sìn Grand Mufti Yorùbá tí Oluwo fi Mùsùlùmí kan jẹ
- Ọwọ́ ọlọ́pàá Cotonou tẹ akọ̀royìn tó fi fọ́nran ohùn Sunday Igboho síta
- Afurasí Sọ́jà kó àwọn akẹ́kọ̀ọ́ TASUED, ìwọ́de gbòde l'Ọ́jọ́bọ̀
- Aṣọ́bodè kan kú, ọ̀kan d'àwátì lẹ́yìn ìkọlù pẹ̀lú afurasí onífàyàwọ́ l'Ogun
- Wàhálà ń bẹ ní Nàíjíríà bí wọn bá tún tako ọmọ onílùú láti wọlé - Soyinka
- Olusegun Mimiko àti ẹgbẹ́ rẹ̀, ZLP darapọ̀ mọ́ PDP
- Ẹ ṣì mí gbọ́ ni, a nílò ìrànwọ́ àwọn ìjọba ìpinlẹ̀ ní ọgbà ẹ̀wọ̀n - Aregbesola
- Obìrin tó ń ta omi inú ọ̀rá subú pẹ̀lú ọmọ lẹ́yìn torí ebi
- Asari Dokubo gbéna wojú IPOB pé ìbò gómìnà yóò wáyé ní Anambra
Pẹlu idajọ yii, awọn aṣoju ẹgbẹ PDP to ti korajọ si gbagede Eagles Square yoo tẹsiwaju ninu ipade ti wọn fẹ ṣe.
Ipade naa yoo waye lọjọ Satide, ọgbọn ọjọ, ati ọjọ Aiku, ọjọ kọkanlelọgbọn, oṣu Kẹwaa, ọdun 2021 yii.
Ko din ni ẹgbẹrun mẹta abọ awọn aṣoju ẹgbẹ oṣelu PDP ti yoo peju sibi ipade ọhun, nibi ti wọn yoo ti yan awọn adari tuntun fun ẹgbẹ naa.
Ọdun 2017 ni Secondus gori alefa gẹgẹ bii alaga ẹgbẹ oṣelu PDP lẹyin to ti kọkọ wa lori oye naa gẹgẹ bii alaga fidihẹ laarin ọdun 2015 si 2016.
Ki lo ti ṣẹlẹ sẹyin?
Ilé ẹjọ́ sún ìdájọ́ síwájú lórí ẹjọ́ tí Secondus pè láti dá ìpàdé gbogbogbò ẹgbẹ́ PDP dúró

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Ile ẹjọ kotẹmilọrun kan niluu Port Harcourt ti sunidajọ rẹ siwaju lori igbẹjọ ti alaga gbogbo ẹgbẹ oṣelu PDP tẹlẹ, Uche Secondus pe tako bi ẹgbẹ naa ṣe ni ko lọ rọkun nile.
Uche Secondus tun n rọ ile ẹjọ naa lati wọgile ipade gbogbogbo ti ẹgbẹ naa mura lati ṣe lọgbọn ọjọ ati ọjọ kọkanlelgbọn oṣu yii tẹsiwaju.
Ṣaaju ni PDP ti kọkọ mu ọgbọn ọjọ ati ọjọ kọkanlelọgbọn oṣu yii fun ipade ti wọn yoo ti yan awọn alaṣẹ tuntun fun ẹgbẹ oṣelu naa lẹyin rogbodiyan to waye ninu ẹgbẹ ọhun ṣaaju, nibi ti wọn ti fi ọwọ osi juwe ile fun igun ẹgbẹ naa ti Secondus n dari.
- Ọkùnrin kan wọ gàù torí ọ̀rọ̀ tó fi ránṣẹ́ sí aya aláya lórí Whatsapp
- Seyi Makinde kò láṣẹ láti fi ẹ̀rọ CCTV sí ọgbà ẹ̀wọ̀n - Aregbesola
- Wọ́n gbé ọmọ mi tó jẹ́ Babaláwo Sunday Igboho, a kò mọ ìrìn rẹ̀ láti oṣù mẹ́ta
- Ṣé lóòtọ́ ni CBN n pín àádọ́ta bílíọnù eNaira lọ́ọ̀fẹ́ fún aráàlú?
- "Ẹlẹ́wọ̀n Abolongo pa méjì lára ọdẹ ìbílẹ̀ lásìkò tà ń ṣà wọ́n kiri ìgboro Oyo"
- Ìwà ìkà sí Yorùbá ni bí ìjọba ṣe ti bodè Seme láti 2019 - Gani Adams
- "Àwa ológun fipá gbàjọba ní Sudan láti dènà ogun abẹ́lé ni"
- Ọmọ onílẹ̀ mẹ́ta kó sí páńpẹ́ ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn
- Wo ohun tí Yinka Alaseyori sọ nipa Tope Alabi ní àyájọ̀ ọjọ́ ìbí rẹ̀
- Ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ àtàwọn èèyàn Sango-Ota ti òpópónà Eko sí Abeokuta pa nítorí ọ̀nà tí kò dára
Ṣugbọn igbesẹ naa ko dun mọ Secondus ninu, eyii to mu ko pe ẹjọ lori bi wọn yọ nipo alaga, ati pe ki ile ẹjọ da ipade naa ti yoo waye duro.
Ṣugbọn ile ẹjọ ti wa sọ pe ẹjọ to pe ko lẹsẹ nilẹ.
Ni bayii, ipade ẹgbẹ oṣelu naa yoo waye lọjọ ti wọn ti da ṣaaju.
Ọdun 2017 ni Secondus gori alefa gẹgẹ bii alaga ẹgbẹ oṣelu PDP lẹyin to ti kọkọ wa lori oye naa gẹgẹ bii alaga fidihẹ lati ọdun 2015 si 2016.














