Osun Masquerade attack: Ìdìtẹ̀, ìpànìyàn, ìfìyàjẹni wà lára ẹ̀sùn tí wọn fi kan àwọn afurasí náà

Awọn Eleegun

Oríṣun àwòrán, Esuleke

Ile ẹjọ majisireti kan nilu Osogbo ti pasẹ ni Ọjọbọ pe ki wọn fi Olori Eleegun, Fashola Esuleke ati Imaamu agba, Kazeem Yunus pẹlu eeyan marun miran si ahamọ.

Eyi ko sẹyin isẹlẹ ikọlu kan to waye ni Mọsalasi Kamarudeen nilu Osogbo laarin awọn Eleegun ati Musulumi, eyi to mu ẹmi olujọsin kan lọ, ti mẹrinla miran si farapa.

Ọjọ Ẹti to kọja, eyiun ọjọ Keji osu Keji ọdun 2021 ni awọn ọlọpaa ti kọkọ fẹ fi oju awọn afurasi naa ba ile ẹjọ amọ Olori Eleegun, Esuleke lo sadede subu, ti wọn ko si le ko wọn lọ sile ẹjọ mọ.

Àkọlé fídíò, 'Ẹ má jẹ́ kí òkú ọmọ mi ráre o ìjọba! Ẹ gbée fún mi kí n lọ sin ín - Ìyá ọmọ ti wọ́n pa ní ìwọ́de Yoruba Nation

Amọ ni Ọjọbọ ni ileesẹ ọlọpaa wọ awọn olujẹjọ meje, eyiun Fashola Esuleke, Kola Adeosun, Idowu Abimbola, Kazeem Yunus, Salawu Jimoh, Alarape Sulaimon Akanbi ati Raimi Saheed lọ sile ẹjọ.

Ẹsun ti wọn si fi kan wọn ni iditẹ, ipaniyan, ifiyajẹni, biba dukia jẹ ati dida alaafia ilu ru.

Àkọlé fídíò, Ó dùn wá gaan pé wọn kò gbé òkú TB Joshua wá sílé, bó ṣe ọgọ́rùn ún ọdún, a ṣì ń retí - Àwọn ìyàwó ilé

Ọlọpaa agbefọba, Taiwo Adegoke lo kede pe awọn afurasi naa wa nile ẹjọ, ti amofin lati ileesẹ eto idajọ, Moses Faremi si n soju fun ijọba.

Lẹyin eyi ni Adegoke wa bẹ ile ẹjọ pe ko fun oun di la lati gba faili ẹjọ awọn afurasi naa, ki oun si se asaro lori rẹ, ki wọn to tun ko wọn pada wa sile ẹjọ.

O salaye pe "Fashola Esuleke, Kola Adeosun ati Idowu Abimbola ni wọn fi ẹsun apaayan kan nigba ti wọn fi ẹsun ifiyajẹni kan Kazeem Yunus, Salawu Jimoh, Alarape Sulaimon Akanbi ati Raimi Saheed."

Agbẹjọro fun Imaamu agba, Kazeem Odedeji wa rọ ile ẹjọ lati gba Kazeem Yunus, Salawu Jimoh, Alarape Sulaimon Akanbi ati Raimi Saheed lati gbadun oniduro wọn ti agọ ọlọpaa fun wọn.

Àkọlé fídíò, 'Ìjámbá Ọ̀kadà ló dédé sọ mi di òdi, ìyàwó tí mo yó ìfẹ́ rẹ̀ náà tún wá jẹ́ odi'

Amọ agbẹjọro fun awọn Eleegun, Kehinde Abioye ni ile ẹjọ nikan lo le sọ nipa oniduro wọn boya ki wọn si wa ni ahamọ ọlọpaa ni tabi ọgba ẹwọn Ilesa.

Adajọ Majisireti to n gbọ naa, Asimiyu Adebayo wa pasẹ pe ki wọn fi awọn olujẹjọ mejeeje si ahamọ ọlọpaa, to si sun igbẹjọ wọn si ọjọ Aje, ọjọ Kejila osu Keje ọdun 2021.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Àkọlé fídíò, Ifayẹmi Elebuibon: Ọ̀pọ̀ òkú ló ń rìn káàkiri ìlú Èkó, Ìbàdàn, Òṣogbo