Grace Oyin Adejobi: Ẹ̀yin òṣèré tíátà lóbìnrin tẹ́ ǹ bọ́ra sí ìhòhò, ẹ sá fún ìtànjẹ́ ayé

Oríṣun àwòrán, Grace Oyin Adejobi
Gbajugbaja osere tiata lede Yoruba, Grace Owoola Oyin Adejobi ti sọ pe ibi tohun ba iṣẹ ere itage de bayii, ohun ko lero wi pe ohun yoo le ṣe ere mọ.
Arabinrin ẹni aadọrun ọdun naa ṣalaye pe, kii ṣe nitori nkankan bi kii ṣe pe agba ti de.
Ninu ifọrọwerọ Iya Oṣogbo lori eto ori redio kan, iyawo agba-ọjẹ oṣere Oyin Adejobi ni, nnkan bii ọdun mẹtadinlaadọta loun bẹrẹ ere ori itage.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Torí ₦300, awakọ̀ ojú omi ṣokùnfà ikú èèyàn méjìlá l‘Eko - Ọlọ́pàá
- Láì san owó oṣù tẹ jẹ wá, kò sọ́rọ̀ kankan - ASUU sọ fún ìjọba
- Ìjọ́ mí ní Italy ni mo fi ń ṣèrànwọ́ fáwọn aṣẹ́wó ọmọ Nàíjíríà tó há - Taribo West
- Ààrẹ orílẹ̀èdè Mali, Boubacar Keita kọ̀wé fipò sílẹ̀
- Àwọn òṣèré tíátà Yorùbá kọjú ìjà síra wọn lórí ìdárò akẹẹgbẹ́ wọn tó kú
- Ìpàkọ́ kò gbọ́ sùtì ní ọ̀rọ̀ ẹ̀yin tí ẹ̀ ń bú mi- Oyedepo
- Mo kọ̀ láti pín ọkọ mi pẹ̀lú ẹnikẹ́ni, nítorí náà ẹ tú wa ká- Abílékọ Idowu faraya ní kóòtù kọkọ-kọkọ
Arabinrin Adejobi wa bẹnu atẹ lu bi awọn oṣere tiata kan paapa awọn obinrin, ti ṣe maa n mura ihoho.
O ni ki wọn maṣe jẹ ki yoroyoro aye tan wọn jẹ, ki wọn si gbagbọ pe ogo Ọlọrun nikan lo le gbe wọn de ipo ọla.
Lara alaye ti Iya Oṣogbo ṣe lori eto naa tun ni ere sinima ti akọle rẹ jẹ Eran Iya Oṣogbo, eyi to fi gba orukọ.
''Mo ti fi orukọ mi lelẹ ṣaaju ki ere Eran Iya Oṣogbo to jade. Kii ṣe ootọ pe ere yii lo gbe ogo mi jade''
Nipa ọjọ manigbagbe nigbesi aye osere yii, Iya Oṣogbo ni ọjọ ti ololufẹ ere awọn kan fẹ ẹ fi ọkọ gba awọn da si gọta nilu Ibadan ni nitori inu rẹ to dun julọ.
''Mi o le gbagbe ọjọ yii nitori pe mo ro pe ọlọjọ lo de ni. Ẹni naa to fẹ ki mi, ki o to ṣeṣi fi ọkọ gba mi wa pada fun mi ẹgbẹrun mẹwa naira to fisi apo iwe''

Oríṣun àwòrán, Grace oyin Adejobi
Lọdun 1953 ni Iya Oṣogbo ni oun bẹrẹ si ni ṣere. Nigba naa lọhun o ni oun a ma ṣere alarinjo kaakiri Naijiria paapa julọ, ni ilu Jebba ni ipinlẹ Kwara.














