TB Joshua burial: Àwọn obìnrin Akoko ní kò sí ọmọbíbí ilẹ̀ náà tó tọ́jú àwọn bíí olóògbé

Oku TB Joshua

Oríṣun àwòrán, Tb joshua ministries/facebook

Bi eto isinku Wolii Temitope Balogun Joshua ṣe ti bẹrẹ lati ọjọ Aje, awọn Iyalaje ati Iyalọja ni ilẹ Akoko nipinlẹ Ondo ti pinnu lati ti gbogbo awọn ọja pa ni ọjọ Ẹti.

Ọjọ Ẹti gan-an ni wọn yoo sin oku oloogbe.

Atẹjade lati ọdọ Iyalaje ti ilu Ikarẹ-Akoko, Alhaja Risikat Mohammed sọ pe awọn ṣe bẹẹ lati bu ọla fun ọmọ wọn to ku.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

O ni ko si ifarada to tobi ju lati fi yẹ ẹ si fun ifẹ, aanu ati oore to ṣe fun awọn eniyan rẹ nigba to wa laye.

O ni eyi yoo tun fun wọn ni anfaani lati wo bi eto isinku naa ba ṣe n lọ lori ẹrọ amohunmaworan ijọ Synagogue, Emmanuel TV.

Àkọlé fídíò, Ó dùn wá gaan pé wọn kò gbé òkú TB Joshua wá sílé, bó ṣe ọgọ́rùn ún ọdún, a ṣì ń retí - Àwọn ìyàwó ilé

Ẹlomii, to jẹ olori fun gbogbo awọn obinrin to jẹ oye ni ilẹ Akoko, Oloye Margaret Ebun Oladunni sọ pe ọsẹ ọfọ ni ọsẹ yii jẹ fun ilẹ Akoko.

O ni ko si ọmọ bibi ilẹ naa to ti ku tabi to wa laye, to ṣe itọju awọn eniyan rẹ bi TB Joshua.

Bayii ni ọja ilu Arigidi sẹ ri lasiko ti akọroyin BBC ṣabẹwo si ilu naa.
Àkọlé àwòrán, Bayii ni ọja ilu Arigidi sẹ ri lasiko ti akọroyin BBC ṣabẹwo si ilu naa.