TB Joshua: Wo nǹkan tó ṣẹlẹ̀ nígbà tí òkú wòlíì yọ sí òṣèrébìnrin, Jaiye Kuti

Oríṣun àwòrán, TB Joshua Ministries and jayeola_monje/Instagram
Gbajugbaja oṣerebinrin, Jaiye Kuti sọ iriri rẹ nipa bi òkú Woli Temitope Joshua ṣe yọ si.
Oṣerebinrin, Jaiye Kuti ni oku oloogbe, Woli Temitope Balogun Joshua, to jẹ oludasilẹ ile ijọsin Synagogue Church of All Nations, yọ si oun lẹyin iku rẹ.
Ninu ọrọ to kọ si ori ayelujara Instagram rẹ, Kuti sọ pe iyalẹnu lo jẹ fun oun pe TB Joshua yọ si oun, bo tilẹ jẹ pe oun ko ri loju koroju ri nigba to wa laye.
- Ayédèrú òṣìṣẹ́ ìjọba ni Baba Ijesha fà kalẹ́ ló jẹ́ kó ṣì wà láhámọ́ - Ọlọ́pàá
- Ìròyìn Yàjóyàjó -'Yinka Alaseyori fèsì sí Tope Alabi fún ìgbà àkọkọ lẹyìn wàhálà orin “Oniduro Mi”, wo ohun tó sọ
- Kí ló dé tí Jaiye Kuti ṣe ń fi omijé ṣe oúnjẹ lọ́pọ̀ ìgbà?
- Pasuma kìí ṣe ọkọ mi o! Lanre Kuti ni mo fẹ́ - Jaiye Kuti
- Irọ́ ni pé àwọn ọ̀gá ọkùnrin ń béèrè fún ìbálòpọ̀ lọ́wọ́ àwọn òṣèrébìnrin- Jaiye Kuti
- Ìjọ Synagogue ti kéde ọjọ́ ìsìnkú TB Joshua pẹ̀lú ibi tí wọn yóò sin ín sí
- Mo rí Áńgẹ́lì mẹ́fà tó wá gbé Wòlíì TB Joshua lọ sọ́run - Àlúfáà kan kéde
- Nǹkan tí a mọ̀ nípa ìlera Asiwaju Ahmed Tinubu
Ọjọ karun-un, oṣu Kẹfa ni Woli naa jade laye lẹni ọdun mẹtadinlọgọta.
Oṣerebinrin naa sọ pe nise ni ori oun dide jan-in lasiko ti oku TB Joshua yọ si oun, ti oun si ri to rọra kọja lọ jẹjẹ.

Oríṣun àwòrán, jayeola_monje/Instagram
"Mi o ri ri lojukoroju, sugbọn oku rẹ yọ si mi nigba to ku.
Emi nikan ni mo wa ninu yara mi ni ilu Offa, ti mo deede ri to kọja. Ori mi dide. Nkankan to dara wa nipa ẹ̀mí naa."
"Alaini ni Kristi, sugbọn o bọ́ awọn eniyan, o si n tọju gbogbo eeyan. Bẹẹ ni ìwọTB Joshua naa ṣe fun ọpọlọpọ.
- Jàǹdùkú ti já ọdún eégún gbà n‘Ibadan, ọ̀pọ̀ ẹ̀mí ti sùn - Ẹgbẹ́ ọlọ́dẹ pariwo
- Iyabo Ojo tún sọ òkò ọ̀rọ̀ sáwọn òṣèré tíátà nínú fídíò tuntun tó gbé síta
- Ìjọba Oyo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní kó àwọn oníbárà kúrò láàrin ìgboro ìlú Ibadan
- Fífẹ́ ọkùnrin ẹgbẹ́ mi jẹ́ ìgbésẹ̀ tó burú ju tí mo gbé láyé
- A ó sọ ibùdókọ̀ ojú irin ìlú Ibadan di gbàgede káràkátà láìpẹ́ - Ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo
- Wo iye owó tí ìjọba Naijiria ti yá lọ́wọ́ China láti ìgbà tí Ààrẹ Muhammadu Buhari ti gorí àléfà
Eeyan meji ni mo mọ to fi aye wọn fun Jesu ni tootọ nipasẹ rẹ̀."
Jaiye Kuti ni oun gbadura pe ki Ọlọrun tẹ Woli T. B Joshua si afẹfẹ rere.
Bakan naa, nigba to n fesi si awọn ọrọ ti awọn ololufẹ rẹ kọ si abẹ awọn nkan to sọ nípa T. B Joshua, paapaa nipa nkan ti awọn eniyan sọ nipa oloogbe nigba aye rẹ.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post
Jaiye Kuti sọ pe awọn erokero naa ko yọ oun silẹ. O ni oun naa gbagbọ bi awọn eeyan ṣe sọ pe Joshua kii ṣe iranṣẹ Ọlọrun tootọ.
"Gbogbo wa la jẹbi awọn ọrọ naa nípa rẹ, nitori pe a ko ri aridaju nipa iru eniyan to jẹ."
Oserebinrin naa wa n beere pe ta ni eeyan Ọlọrun gan bikose ẹni to se awọn ofin rẹ, to si jẹ pe awọn ojisẹ Ọlọrun nkan wa, to jẹ pe owo ni wọn n wa.
"Wọn ko ni fi ọrọ Ọlọrun gan bọ wa debi pe a mọ ẹni ti Ọlọrun jẹ, okoowo ni wọn n fi ẹsin Kristiẹni se.
Ni Italy, wọn maa fun wa lowo tori pe a wa sile ijọsin, wọn yoo fun wa lowo lati wa sin Ọlọrun ni amọ nibi yii, ohun gbogbo ta ni la fi n sin awọn ojisẹ Ọlọrun."
O fikun pe ọpọ eeyan ni ko mọ ofin orilẹede yii amọ wọn le ka bibeli lori lati ibẹrẹ de opin.
O wa kede pe wọn kan n fi ẹsin tu wa jẹ lasan ni, to si jẹ pe ọtẹ ati tẹmbẹlẹkun lo kun inu ọpọ eeyan to n fi ara rẹ we Kristi.






















