Olubadan in Council: Ìṣẹ̀ṣe àti àwọn ìgbésẹ̀ wọ́nyìí ní a máa fi yan Olubadan tuntun- Ìgbìmọ̀ Olubadan

Oríṣun àwòrán, Others
Àwọn mẹ́wàá nínú ìgbìmọ̀ ẹlẹ́ni mọ́kànlá to jẹ Afọbajẹ ni ìlú Ìbàdàn ti buwọ́lu yiyan Senetọ Lékan Balógun gẹ́gẹ́ bíi Olúbàdàn tuntun.
Ìgbìmọ̀ ọ̀hún tún làá mọ́lẹ̀ pé awuyewuye tó ń wáyé kò lè dínà ẹni tí oyè tọ́ sí gẹ́gẹ́ bí Olúbàdàn láti bọ́ sí orí àpèrè.
Olóyè Òsì Balógun ìlú Ìbàdàn, Tajudeen Ajíbọ́lá ló sọ èyì fùn àwọn akọ̀ròyìn l'ọ́jọ́ Rú.
- Lẹ́yìn wákàtí mẹ́ta tí wọ́n kéde pé ìyá mi kú, ó tún mi ọwọ́ rẹ̀ ooo - Ọmọ Iyabo Oko
- Sanwo-Olu ṣèlérí láti ṣiṣẹ́ lórí àbọ̀ ìgbìmọ̀ olùwádìí ilé alájà 21 tó wó ní Ikoyi
- Àwọn akẹgbẹ́ Gómìnà Sanwo-Olu f'ohùn sílẹ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ìdójútini tó ṣẹlẹ̀ sí i lọ́wọ́ ọlọ́pàá ní Magodo
- Afenifere,PDP, Ohaneze sọ̀kò ọ̀rọ̀ sí Buhari lórí ọ̀rọ̀ tó sọ nípa ètò ààbò
- Erin tẹ obìnrin kan àti ọmọ rẹ̀ pa lọ́jọ́ ọdún
Olóyè Tajudeen Ajíbọ́lá ní gẹ́gẹ́ bí àṣà ìlú Ìbàdàn, olóyè Balógun ni Olúbàdàn kàn.
Bákan náà ló fi kun un pé koko lara ọta olóyè Balógun le wí pé irọ̀ tó jìnà sí òótọ́ ni pé òjòjò ń ṣe ògún rẹ̀.
Ó ní àhesọ lásán ni gbogbo awuyewuye tó ń lọ lórí ẹ̀rọ ayélujára.
Kini A'sa ilu Ibadan sọ nipa yiyan Olubadan tuntun?
Ni ọpọlọpọ ilu ni ilẹ yoruba, ifa ni o ma n ṣe itọni sọnọ lori ẹni ti o maa jọba lẹyin ti ọba kan ba gbesẹ.
Amọ ni ilu Ibadan, gbogbo ọmọ ilu ni o lẹtọ ati jẹ Olubadan.
Oun ti ọ se pataki ni ki ẹni naa jẹ oloye ti osi ma gun akasọ to yẹ ki o to di Olubadan.
Ọna meji ti wọn gba gun akasọ ki wọn to di Olubadan ni lati idi Ẹgbẹ agba ati Ẹgbẹ Balogun.
Ti Olubadan bati gbesẹ, eni to ba kan ninu awọn Oloye agba lati idi mejeeji ni wọn maa de lade gẹgẹ bi Ọba titun.
Amọ, tito ni wọn ma n to laarin idi mejeji náà nitori pe ti Olubadan kan ba jẹ lati idi ẹgbẹ Agba, ẹgbẹ Balogun ni Olubadan ti yoo jẹ lẹyin rẹ yoo ti wa.
Lati idi ẹgbẹ agba, ipo Jagun ni akasọ akọkọ lẹyin naa ni Akasọ mọkanlelogun (21) ki oloye naa to di Olubadan.
Lati idi ẹgbẹ Balogun, akasọ mejilelogun (22) ni o ṣẹ pataki ki enikeni o gun ko to le di Olubadan lẹyin ti o ba tijẹ oye Jagun.
Olubadan to ṣẹṣẹ gbesẹ, Oba Saliu Adetunji, ni o di Olubadan lẹhin ọdun mejidinlogoji tojẹ oye Jagun.
- Ìjọba Nàìjíríà kéde àwọn agbébọn gẹ́gẹ́ bíi agbésùnmọ̀mí káàkiri Nàìjíríà- Malami
- Ẹlẹ́wọ̀n méjì kú, wọ́dà farapa lásìkò tí àwọn ẹlẹ́wọ̀n fẹ́ sálọ ní Ile-Ife
- Adigunjalè kọlu Kemi Afolabi, wọ́n fi àdá ṣá òun àti awakọ̀ rẹ̀
- Àwọn òṣìṣẹ́ RUGIPO ti bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì àìlópin
- Mọ̀ síi nípa àwọn ọjọ́ tó yàtọ̀ àti àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó wà nínú àkọsílẹ̀ láti ṣẹlẹ̀ lọ́dún yìí
- Nkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa Bello Turji, afurasí bálógun ajínigbé ní Ariwa Naijiria
Ìṣẹ̀ṣe, Àṣà àti àwọn ìgbésẹ̀ wọ́nyìí ní a máa fi yan Olubadan tuntun....- Ìgbìmọ̀ Ìṣèjọba Olubadan
Báyìí ni aṣẹ ma yan Olubadan titun oo- Olubadan-in-Council
Igbimọ iṣejọba Olubadan, iyen Olubadan-in-Council ti sọ pe awọn yoo tẹle aṣa ilu Ibadan lati yan Olubadan titun bo tilẹ jẹ pe àwọn ti jọba tẹlẹ rí.
Wọn ni Aṣa ati Iṣẹṣẹ lagba gbogbo eniyan.
- Oloye Ladoja nìkan ló le sọ bóyá Lekan Balogun yòó di Olubadan tuntun-Moses Orogade
- Èsì àyẹ̀wò òkú Sylvester Oromoni kò fihàn pé ẹnikẹ́ni ló pa á - Kọmiṣọnna ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Eko
- IPOB fòfin dè kíkọ orin ògo Nàìjíría láwọn ilé ẹ̀kọ́ gúúsù ìlà oòrùn Nàìjíríà nítorí pé...
- Ọwọ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ogun tẹ Wasiu Eluyẹra tó fẹ́ pa ìyàwó rẹ̀ tẹ́lẹ̀ nítorí pé ó lóyún
- Koiki àti Olajengbesi ń jíṣẹ́ ara wọn ni, Igboho kọ́ ló rán wọn níṣẹ́, Agbẹjọ́rò Sunday Igboho faraya
Iroyin yi ni wọn fi lede lẹyin ti wọn ṣe ipade ni ile Oloye àgbà Lekan Balogun ti o jẹ Ọtun Olubadan.
Amọ, Oloye giga Rashidi Ladọja ti o jẹ gomina tẹlẹ ni ipinlẹ Ọyọ ati ọmọ ẹgbẹ igbimọ asejọba Olubadan pẹlu awọn meji miran ni ko kopa ninu ipade naa.
Lẹyin ipade ọun, oloye Balogun salaye pe lẹyin ti wọn ba ti ṣọfọ Ọba Saliu Adetunji tan, wọn yio ṣe ipade mii lati kede Olubadan titun gẹgẹ bi aṣa ilu Ibadan.
Lekan Balogun ṣalaye pe kosi laasigbo lori ẹni ti yio jẹ olubadan titun o.
O fi kun ọrọ rẹ pe igbega awọn ọmọ igbimọ naa si ọba ko ṣe idiwọ fun aṣa ati iṣe iṣembaye yiyan olubadan titun sipo.
Balogun wa fi da awọn ọmọ Ibadan nile loko loju pe kosi ewu loko nitori pe gẹgẹ bi afọbajẹ ilu Ibadan, awọn yio ṣe ohun totọ lasiko toyẹ.


















