Yọmi Alliyu tó jẹ́ agbẹjọ́rò Oloye Sunday Igboho ti sọ̀rọ̀sókè lórí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ láàrin Koiki àti Pelumi Olajengbesi pé ó tó gẹ́!

Oríṣun àwòrán, @Sunday Igboho
Lori edeaiyede to n waye bayii lagbo awọn ajijagbara fun Yoruba nation, agbẹjọro fun Sunday Igboho, Yọmi Aliyu ti sọ pe eekan aṣiwaju ipe fun idasilẹ orilẹede Yoruba labẹ aṣia Yoruba Nation, Oloye Sunday
Igboho ko fi iṣẹ ran ẹnikẹni to ba n sọ ohunkohun fun araye gbọn bayii labẹ iboju pe ọrọ ti Oloye Igboho fi ran oun sawọn eeyan ni kan n parọ lasan ni.
Amofin agba Yọmi Alliyu SAN, ṣalaye ninu atẹjade kan to fi sita pe ko si ẹnikẹni to lee gbẹnusọ fun Oloye Sunday Igboho ju awọn tawọn jẹ agbẹjọro rẹ lọ.
- 'Pelumi Olajengbesi kìí ṣe agbẹjọ́rò Sunday Igboho, Ilana Omo Oodua ló gbà á ṣíṣẹ́'
- Wọ́n ti sin òkú Alhaji Bashir Tofa ni Kano báyìí
- Olóòtú ìjọba Sudan, Abdalla Hamdok ti kọ̀wé fipò rẹ̀ sílẹ̀ lẹ́yìn ìwọ́de àwọn ará ìlú
- Gomina Wike fi òfin de iṣẹ́ aṣẹ́wó, Night Club, kátàkárà alẹ́ àti àwọn nkan míràn
- Ṣé lóòtọ́ ni wọ́n rọ Oba Ijeru, Onpetu Sunday Oladapo lóyè?
- Ta ni Oloye Lekan Balogun tí aráyé ń pariwo pé òun ni Olubadan ilẹ̀ Ibadan kàn?
- Wọ́n ti gbé Olubadan wọ káà ilẹ̀, bí ìsìnkú Ọba Adetunji ṣe lọ nìyí
Gẹgẹ bi o ṣe sọ, alaye naa ṣẹlẹ nitori iroyin kan to jade sigboro aye pe amofin Pẹlumi Ọlajẹngbesi to jẹ agbẹjọro fun awọn eeyan mejila ti wọn ko nile Sunday Igboho.
Oṣu keje ọdun 2021 ni wọn ko wọn nibẹ.
Olajengbesi wa sọ pe oun jawọ lori gbigbọ́ ẹjọ ro fun Oloye Sunday Igboho.
Amofin Agba Ymi Aliyu sọ pe, ati Koiki to n pe ara rẹ lagbẹnusọ Sunday Igboho ati amofin Pẹlumi Ọlajengbesi to ni oun kọwe fi iṣẹ gbigba ẹjọ rẹ ro, ko si eyikeyi to laṣẹ lati gbẹnusọ fun Sunday Igboho ninu wọn.
- Wo ohun tó ń ṣẹlẹ̀ báyìí ní ilé Oloye Lekan Balogun tí wọ́n n sọ pé oyè Olubadan kàn
- Ta ni Oloye Lekan Balogun tí aráyé ń pariwo pé òun ni Olubadan ilẹ̀ Ibadan kàn?
- Gomina Wike fi òfin de iṣẹ́ aṣẹ́wó, Night Club, kátàkárà alẹ́ àti àwọn nkan míràn
- Iléewòsàn UCH kò lè bá Aafin Ibadan parọ́, ẹ dẹ́kún gbígbé ìròyìn òfegè nípa Oba Adetunji tó wàjà- Adeola Oloko
- Ọmọkùnrin kan bẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin tó lóyún lórí nítorí pé...
Amofin Aliyu SAN ni Gbogbo ohun ti wọn ba n sọ lori Igboho, Iṣẹ ara wọn ni wọn n jẹ ki araalu maṣe kbi ara si wọn.
Aliyu ni lootọ odi ọrọ ni Adari ẹgbẹ Ilana Ọmọ Oodua, Ọjọgbọn Banji Akintoye sọ nigba to n wi pe ko ni si idibo ni ipinlẹ Ekiti ati Ọṣun.
O ni ki araalu maṣe tẹti si gbogbo ọrọ ti Koiki ati Ọlajẹngbesi n sọ nigboro pe Oloye Sunday lo ran awọn.

















