Gomina Wike fi òfin de iṣẹ́ aṣẹ́wó, Night Club, kátàkárà alẹ́ àti àwọn nkan míràn

Nyesom Wike

Oríṣun àwòrán, NYESOM WIKE/FACEBOOK

Gomina ipinlẹ Rivers, Nyesom Wike ti fofin de iṣẹ aṣẹwo ati ile ijo 'Night Club' nipinlẹ naa.

Ninu ọrọ to ba awọn eniyan ipinlẹ Rivers sọ fun ọdun tuntun lo ti kede pe ko gbọdọ si kara-kata ni alẹ mọ, to fi mọ awọn aṣẹwo to n duro ni ẹ́gbẹ́ titi, paapaa ni awọn adugbo bii Abacha road ati awọn opopona to yi i ka bi Casablanca.

O ni aṣẹ tuntun yii yoo fi opin si ipa buruku ti iṣẹ ainitiju yii n ni lara ihuwasi awọn ọmọde ati awujọ ni apapọ.

Yatọ si eyi, Gomina Wike tun kede pe ijọba yoo gba awọn ilẹ ti ko si ile lori wọn ati awọn ile akọ pati to wani GRA nilu Port Harcourt ati Obio Akpor.

Gomina sọ pe igbesẹ na yoo waye nitori pe awọn ọdaran ti n lo wọn fun iṣẹ ibi.

Àkọlé fídíò, 'Òṣìṣẹ́ Bánkì ni mí l'Amẹ́ríkà kí n tó bẹ̀rẹ̀ Tíátà'

Ijọba ni yoo si ta awọn ilẹ naa fun awọn to ṣetan lati kọ ile sori wọn ni kiakia.

Bakan naa lo tun paṣẹ fun awọn alaga ijọba ibilẹ pe ki wọn o ṣiṣẹ pọ pẹlu awọn olori agbegbe lati mọ awọn to ni ibudo ifọpo ti ijọba ko fọwọ si.

Àkọlé fídíò, Ọdún tó súnmọ́ ìdìbò ni 2022, wọ́n ó ni ta ẹ̀jẹ̀ wa sílẹ̀

Lati asiko diẹ ni awọn eeyan ilu Port Harcourt ti n ke irora lori bi gbogbo inu ile wọn, ọkọ to fi mọ ẹya ara wọn ṣe n dudu nitori eefin to n jade lati awọn ibudo ifọpo naa.

Wike sọ pe ijọba oun yoo bẹrẹ si ni kọju ija si awọn eniyan naa bayii, nitori pe ijọba apapọ ko dahun si iwe ti oun kọ si lati fi opin si iṣẹ awọn ibudo ti wọn ti n fọ eporọbi, ti ijọba ko fi ọwọ si.

Awọn ofin miran to tun sẹ fun ọdun tuntun ni pe ijọba yoo ma a gbẹsẹ le ọkọ ti wọn ba gbe si ojupopo ju wakati mejidinlaadọta lọ. Bakan naa ni ijọba yoo tun wó awọn ile ti wọn kọ si oju àgbàrá.

O kede pe ijọba oun yoo gbe ajọ alaabo kogberegbe kalẹ lati ma a fi ofin mu awọn toba ru awọn ofin tuntun.

Àkọlé fídíò, Prophet Hezekiah New Year Prayer: Gbogbo wa ni ká ṣiṣẹ́ fún ìdàgbàsókè Naijiria