Bashir Othman Tofa: Wọ́n ti sin òkú Alhaji Bashir Tofa ni Kano báyìí

Wọn ti sin oku Alhaji Bashir Tofa oludije fun ipo aarẹ orilẹede Naijiria nigbakan ri.
Ẹni ọdun mẹrinlelaadọrin ni Tofa, wọn sin in ni ilana musulumi lẹyin to jade laye lọjọ Aje, ọjọ kẹta osu kini ọdun 2021.
- 'Pelumi Olajengbesi kìí ṣe agbẹjọ́rò Sunday Igboho, Ilana Omo Oodua ló gbà á ṣíṣẹ́'
- Olóòtú ìjọba Sudan, Abdalla Hamdok ti kọ̀wé fipò rẹ̀ sílẹ̀ lẹ́yìn ìwọ́de àwọn ará ìlú
- Gomina Wike fi òfin de iṣẹ́ aṣẹ́wó, Night Club, kátàkárà alẹ́ àti àwọn nkan míràn
- Ta ni Oloye Lekan Balogun tí aráyé ń pariwo pé òun ni Olubadan ilẹ̀ Ibadan kàn?
- Iléewòsàn UCH kò lè bá Aafin Ibadan parọ́, ẹ dẹ́kún gbígbé ìròyìn òfegè nípa Oba Adetunji tó wàjà- Adeola Oloko
Ni ile rẹ to wa ni agbegbe Gandul Albasa nilu Kano ni adura ni ilana musulumi ti waye.
Emir ti ilu Kano, Aminu Ado Bayero ati ọpọlọpọ awọn eeyan ni wọn peju si ibi adura naa ki wọn to lọ sin oku rẹ si itẹ kan nilu Kano.

Alhaji Bashir ni oludije to ba Oloogbe MKO Abiọla du ipo aarẹ orilẹ-ede Naijiria lọdun 1992.
Kounsilo ni Tofa fi bẹrẹ iselu ni ijọba ibilẹ Dawakin Tefa ni odun 1977

Tofa du ipo aarẹ labẹ aṣia ẹgbẹ oṣelu National Republican Convention, NRC nigba ti MKO Abiola dije labẹ aṣia ẹgbẹ oṣelu SDP.
Saaju iku rẹ, Tofa jẹ alaga igbimọ agba ipinlẹ Kano













