Bandits Proscribed as terrorists: Ìjọba Nàìjíríà kéde àwọn agbébọn gẹ́gẹ́ bíi agbésùnmọ̀mí káàkiri Nàìjíríà

Oríṣun àwòrán, Others
Ijọba Naijiria ti kede awọn agbebọn sọṣẹ gẹgẹ bi asẹrubalu
Kini omaa wa sẹlẹ si wọn bayii?
Ikede yii lo wa ninu iwe atunse ofin 'Gazette" ti ijọba apapọ filede, to fi ofin de ẹnikẹni tabi ẹgbẹkẹgbẹ lati mase lọwọ ninu iwa awọn asẹrubalu yiiNkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa Bello Turji, afurasí bálógun ajínigbé ní Ariwa Naijiria

Oríṣun àwòrán, @Min of Information
- Wo àwọn agbábọ́ọ̀lù Nàìjíríà tó ti dé fún ìgbáradì àti ibi tí ọ̀rọ̀ dé dúró lóri AFCON 2022
- Lẹ́yìn wákàtí mẹ́ta tí wọ́n kéde pé ìyá mi kú, ó tún mi ọwọ́ rẹ̀ ooo - Ọmọ Iyabo Oko
- Adigunjalè kọlu Kemi Afolabi, wọ́n fi àdá ṣá òun àti awakọ̀ rẹ̀
- Erin tẹ obìnrin kan àti ọmọ rẹ̀ pa lọ́jọ́ ọdún
- Nkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa Bello Turji, afurasí bálógun ajínigbé ní Ariwa Naijiria
- Ọwọ́ Ọlọ́pàá ti tẹ̀ Obìnrin ọlọ́pàá tó kí ọwọ́ ọmọ tó ń gbé pẹ̀lú rẹ̀ bọ omi gbígbóná nítorí pé o jí ẹran jẹ lásìkò ọdún Kérésìmesì

Oríṣun àwòrán, @Min of Information
Ojọ ru, ọjọ karun un, oṣu kinni, ọdun 2022 ni ijọba gbe iwe ofin kale ti agbẹjọ agba ati minista fun eto idajọ, Abubakar Malami bu ọwọ lu.
Eleyi lo wa lẹyin ti Ile-ẹjọ giga ni ilu Abuja kede awọn agbebọn yii gẹgẹ bi asẹrubalu.
Ninu idajọ ile-ẹjọ naa ni osu kọkanla, odun 2021, Onidajọ Taiwo Taiwo fidi ẹ mulẹ wi pe isesi awọn ẹgbẹ Yan Bindiga and Yan Ta'adda jẹ iwa isẹrubalu.
Ile-isẹ apapọ to n risi ọrọ idajọ ni o gbe ẹjọ yii losi waju onidajọ Taiwo.
Kini atupalẹ iwe atunse ofin 'Gazette' yii sọ?
Ikede náà sọ di mimo wipe àwọn egbe bii Yan Bindiga, ati Yan Ta'adda ati awọn ẹgbẹ miiran to dàbí rẹ ni wọn ti f'ofin de ni gbogbo orileede Naijiria.
Ofin naa fi kun un pe paapaa ju lọ ni ẹkun ariwa Iwo Oorun ati aarin gbungbun ariwa ni orilede Naijiria ni ofin naa de awọn agbebọn serubalu yii.
Eleyi lo wa ni ibamu pẹlu abala kini ati ìkejì ofin isẹrubalu tọdun 2011.
Tani awọn agbebọn yii gan an?
Awon agbebon ti wọn maa n saba fara pamọ si inu igbo ti wọn ti kọtì lati s'ọse ni awọn ilu ati ileto ni ẹkun Ariwa-Iwọ Oorun.
Wọn ti wa darapọ mọ awọn ẹgbẹgun ajinigbe lati gba owo idasilẹ.
Lati bi ọdun mẹwa bayii, o lẹ ni ẹgbẹrun mẹjọ eyan ti wọn ti ku ni awọn ipinlẹ bii Kebbi, Sokoto, Niger ati Zamfara, gẹgẹ bi akọsilẹ ajọ agbaye ton s'akọsilẹ ìkogun jani.
Awọn akọlu wọnyii ni a le lọdi rẹ mọ ede aiyede latẹyinwa laarin awọn Fulani darandaran ati awọn agbegbe ti awọn eeyan kan ya sọtọ lati soko.
- Wọ́n ti gbé Olubadan wọ káà ilẹ̀, bí ìsìnkú Ọba Adetunji ṣe lọ nìyí
- Ọmọkùnrin tó fẹ́ kọ́ṣẹ́ Yahoo wá sọ́dọ̀ wa lẹyìn tó mu Colorado tán ló bá kú- Afurasí ọmọ Yahoo
- Wo ohun tó ń ṣẹlẹ̀ báyìí ní ilé Oloye Lekan Balogun tí wọ́n n sọ pé oyè Olubadan kàn
- Gomina Wike fi òfin de iṣẹ́ aṣẹ́wó, Night Club, kátàkárà alẹ́ àti àwọn nkan míràn
- 'Pelumi Olajengbesi kìí ṣe agbẹjọ́rò Sunday Igboho, Ilana Omo Oodua ló gbà á ṣíṣẹ́'


















