Afcon 2022: Àwọn agbábọ́ọ̀lù mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n tí balẹ̀ sí ibùdó ìgbáradì ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Super Eagles

Oríṣun àwòrán, @NFF
Ahmed Musa, Odion Ighalo, Kelechi Iheanacho wà lára àwọn agbábọ́ọ̀lù mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n lo tí balẹ̀ sí ibùdó ìgbáradì ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Super Eagles ni ìgbáradì fún ìdíje ife ẹ̀yẹ Africa Cup of Nations (AFCON).
Àwọn agbábọ́ọ̀lù mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n lo tí balẹ̀ sí ibùdó ìgbáradì ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Super Eagles ni ìgbáradì fún ìdíje ife ẹ̀yẹ Africa Cup of Nations (AFCON).
Ìdíje AFCON yóò wáyé fun oṣù bẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ Àìkú, ọjọ́ kẹsàn-án, oṣù Ṣẹẹrẹ títí di ọjọ́ kẹfà, oṣù Èrélé, ọdún 2022 ní orílẹ̀ èdè Cameroon.
- Oloye Ladoja nìkan ló le sọ bóyá Lekan Balogun yòó di Olubadan tuntun-Moses Orogade
- Ká má rí! Kò sí aàyè fún ìdìbò Gómìnà ní Osun àti Ekiti- Ilana Omo Oodua
- Ìṣẹ̀ṣe, Àṣà àti àwọn ìgbésẹ̀ wọ́nyìí ní a máa fi yan Olubadan tuntun....- Ìgbìmọ̀ Ìṣèjọba Olubadan
- Èsì àyẹ̀wò òkú Sylvester Oromoni kò fihàn pé ẹnikẹ́ni ló pa á - Kọmiṣọnna ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Eko
- IPOB fòfin dè kíkọ orin ògo Nàìjíría láwọn ilé ẹ̀kọ́ gúúsù ìlà oòrùn Nàìjíríà nítorí pé...
- Ọwọ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ogun tẹ Wasiu Eluyẹra tó fẹ́ pa ìyàwó rẹ̀ tẹ́lẹ̀ nítorí pé ó lóyún
- Koiki àti Olajengbesi ń jíṣẹ́ ara wọn ni, Igboho kọ́ ló rán wọn níṣẹ́, Agbẹjọ́rò Sunday Igboho faraya
Ìròyìn fi yé wa pé àwọn agbábọ́ọ̀lù mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n lo tí balẹ̀ sí ibùdó ìgbáradì nínú àwọn méjìdínlọ́gbọ̀n tí akọ́nimọ̀ọ́gbá fìdíẹ́ fún ikọ̀ Super Eagles, Augustine Eguavoen ráńṣẹ́ sí láti kópa nínú ìdíje náà.
Ní ọjọ́ Ọjọ́rú tó ń bọ̀ yìí ni ikọ̀ Super Eagles yóò fi orílẹ̀ èdè Nàíjíríà sílẹ̀ lọ sí orílẹ̀ èdè Cameroon.
Ẹwẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn agbábọ́ọ̀lù ikọ̀ Super Eagles láti ilẹ̀ òkèerè ló ṣì ń wọ ibùdó ìgbáradì lásìkò tí à ń kó ìròyìn yìí jọ.
Èyí ló ń wáyé lẹ́yìn oṣù kan tí àjọ NFF ti fi orúkọ àwọn agbábọ́ọ̀lù tí wọ́n ráńṣẹ́ sí léde.
- Wo ohun tó ń ṣẹlẹ̀ báyìí ní ilé Oloye Lekan Balogun tí wọ́n n sọ pé oyè Olubadan kàn
- 'Pelumi Olajengbesi kìí ṣe agbẹjọ́rò Sunday Igboho, Ilana Omo Oodua ló gbà á ṣíṣẹ́'
- Iléewòsàn UCH kò lè bá Aafin Ibadan parọ́, ẹ dẹ́kún gbígbé ìròyìn òfegè nípa Oba Adetunji tó wàjà- Adeola Oloko
- Wọ́n ti gbé Olubadan wọ káà ilẹ̀, bí ìsìnkú Ọba Adetunji ṣe lọ nìyí
- Ọmọkùnrin kan bẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin tó lóyún lórí nítorí pé...
- Ṣé lóòtọ́ ni wọ́n rọ Oba Ijeru, Onpetu Sunday Oladapo lóyè?
Bákan náà, àwọn agbábọ́ọ̀lù mìíràn ń fi ibùdó ìgbáradì sílẹ̀ látaàrí ìfarapa àti àìsàn.
Gẹ́gẹ́ bí àlàyé àjọ Confederation of African Football (CAF), rẹfirí mẹ́rìnlélógún àti igbákejì rẹfirí mọ́kànlélọ́gbọ̀n láti orílẹ̀ èdè mẹ́rìndínlógójì ni yóò kópa nínú ìdíje náà.
Orílẹ̀ èdè Nàíjíríà, Egypt , Sudan àti Guinea Bissau tó ń ṣẹ̀ṣẹ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́ ló wà nínú gúrùupù kan náà.
Awon ti wọn pee ree ati orukọ ẹgbẹ agbabọọlu ti wọn n gba bọọlu fun ki Naijiria to ranṣẹ si wọn:
Adilemu:
Francis Uzoho (AC Omonia, Cyprus)
John Noble (Enyimba FC)
Daniel Akpeyi (Kaizer Chiefs, South Africa)
Maduka Okoye (Sparta Rotterdam, The Netherlands)
Atamatase:
Ahmed Musa (Fatih Karagumruk, Turkey)
Henry Onyekuru (Olympiacos FC, Greece)
Moses Simon (FC Nantes, France)
Sadiq Umar (UD Almeria, Spain)
Taiwo Awoniyi (Union Berlin, Germany)
Alex Iwobi (Everton FC, England)
Peter Olayinka (SK Slavia Praha, Czech Republic)
Kelechi Iheanacho (Leicester City, England)
Awọn Agbbọọlu laarin lori Papa
Frank Onyeka (Brentford FC, England)
Wilfred Ndidi (Leicester City, England)
Chidera Ejuke (CSKA Moscow, Russia)
Kelechi Nwakali (SD Huesca, Spain)
Awọn Agbabọọlu to n di ẹyin ile mu:
Chidozie Awaziem (Alanyaspor FC, Turkey)
Kenneth Omeruo (CD Leganes, Spain)
Oluwasemilogo Ajayi (West Bromwich Albion, England)
William Ekong (Watford FC, England)
Olaoluwa Aina (Torino FC, Italy)
Zaidu Sanusi (FC Porto, Portugal)
Olisa Ndah (Orlando Pirates, South Africa)
Awon miran ti wọn tun pe ni:
Jamilu Collins (SC Padeborn 07, Germany)
Tyrone Ebuehi (Venezia FC, Italy)
Joseph Ayodele-Aribo (Glasgow Rangers, Scotland)
Samuel Chukwueze (Villarreal FC, Spain)
Odion Jude Ighalo (Al-Shabab Riyadh, Saudi Arabia)



















