Yoruba Nation: Ká má rí! Kò sí aàyè fún ìdìbò Gómìnà ní Osun àti Ekiti- Ilana Omo Oodua

Oríṣun àwòrán, Others
Bi ileri Ilana Omo Odua ba file di imusẹ, o seese ki idibo Gomina to yẹ ko waye nipinlẹ Osun ati Ekiti lọdun yi ma waye rara.
Egbẹ ọmọ Yoruba yi labẹ akoso ọjọgbọn Banji Akintoye sọ pe idibo kankan ko ni waye lawọn ipinlẹ mejeeji yi.
INEC n palẹmọ idibo ni Ekiti nibi ti Gomina Kayode Fayemin kogba saa keji rẹ nile ati Osun nibi ti Gomina Gboyega Oyetola ti fẹ dije dupo saa keji.
- Oloye Ladoja nìkan ló le sọ bóyá Lekan Balogun yòó di Olubadan tuntun-Moses Orogade
- IPOB fòfin dè kíkọ orin ògo Nàìjíría láwọn ilé ẹ̀kọ́ gúúsù ìlà oòrùn Nàìjíríà nítorí pé...
- Koiki àti Olajengbesi ń jíṣẹ́ ara wọn ni, Igboho kọ́ ló rán wọn níṣẹ́, Agbẹjọ́rò Sunday Igboho faraya
- 'Pelumi Olajengbesi kìí ṣe agbẹjọ́rò Sunday Igboho, Ilana Omo Oodua ló gbà á ṣíṣẹ́'
- Gomina Wike fi òfin de iṣẹ́ aṣẹ́wó, Night Club, kátàkárà alẹ́ àti àwọn nkan míràn
- Olóòtú ìjọba Sudan, Abdalla Hamdok ti kọ̀wé fipò rẹ̀ sílẹ̀ lẹ́yìn ìwọ́de àwọn ará ìlú
Ọjọgbọn Akintoye ninu ọrọ ikini ọdun 2022 sọ pe laarin awọn ajijagbara Yoruba erongba papọ lori pe ki idibo ile asofin ati Gomina ma se waye nilẹ kaarọ o jiire.
O ni: ''Idibo akọkọ ti a fẹ se leleyi ti a o se ninu orileede tiwa gan an''
Kaakiri ni Ọjọgbọn Akintoye ti n lewaju ipolongo iwọde ti wọn fi n pe fun idasilẹ Yoruba Nation pẹlu ajijagbara nii Sunday Adeyemo Igboho.
O sọ pe ''ọkan wa balẹ pe orileede Yoruba taa n wa ti de tan.
Nitori naa, ẹ jẹ ki a maa ronu lori nkan ti yoo mu ki ilẹ wa jẹ ibi to dara julọ lati gbe lagbaye.
Ati pe ẹ jẹki a maa ronu nipa awọn nkan ti yoo sọ orileede di ọrẹ atioluranlọwọ awọn alabagbe wa''
Igba akọkọ ree ti Ilana Omo Odua yoo fi fi ọrọ lile silẹ pe awọn yoo tako eto isejọba bi idibo nilẹ Yoruba.
Ọrọ ikini ọdun ti alagba Banji Akintoye si ti sọ ọrọ yi jẹ ọna kn gboogi ti ikọ ajijagbara IPOB naa lo lati fi sọ laipẹ yi pe awọn ko fẹ ki awọn akẹkọọ maa ka orin orileede Naijiria nile ẹkọ mọ.
Ko daju boya wọn fẹ fi ipa di idibo yi lọwọ ni tabi pe wọn yoo se iwọde ni itako awọn orisi ifiyajẹni ti wọn ni awọn Ypruba n koju labẹ ijọba to wa lode yi.
Ọkan pato ninu ẹhonu wọn ni bi wọn se ni ogunagbongbo ọmọ Yoruba nii, Sunday Adeyemo Igboho ti se n koju ipenija orisirisi lọwọ ijọba amunisin.
Wọn ni bẹrẹ lati igba ti ijọba Naijiria fi se ikọlu si ile rẹ to wa ni Ibadan pẹlu ikọ ajọ ọtẹlẹmuyẹ ni Sunday Igbohho ko ti ri isinmi.
Ohun nikan kọ ni wọn darukọ, wọn ni ''ọmọ ile Ekiti kan naa ti wa ni ahamọ fun aimọye osu lati igba ti ikọlu ile Sunday Igboho ti waye.
Ko ba ku si ahamọ, ọpọlọpẹ Eledumare to pa a mọ.
Bẹrẹ lati ọdun 2022, a setan lati gbe awọn igbesẹ to lagbara lati tako ifiyajẹni awọn eeyan wa''


















