Lekan Balogun next Olubadan: Oloye Agba, Adewolu Ladoja nìkan ló lè sọ bóyá Oloye Lekan Balogun yóò gun orí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bíi Olubadan tuntun

Ladoja ati Lekan Balogun

Oríṣun àwòrán, Others

Kii ṣe tuntun mọ pe iroyin ti n lọ kaakiri igboro pe Oloye Agba, Lekan Balogun ni oye Olubadan ilẹ Ibadan kàn Wọ́n ti gbé Olubadan wọ káà ilẹ̀, bí ìsìnkú Ọba Adetunji ṣe lọ nìyí

Ṣugbọn bi iroyin naa ṣe n lọ, ni awọn kan tun n sọ pe oye naa ko tọ si i.Ta ni Oloye Lekan Balogun tí aráyé ń pariwo pé òun ni Olubadan ilẹ̀ Ibadan kàn?

Amofin kan, Moses Orogade, sọ pe Oloye Agba Adewolu Ladoja nikan lo le sọ boya Oloye Lekan Balogun yoo gun ori itẹ gẹgẹ bi Olubadan tuntun.

Ṣaaju ni Amofin kan ti sọ pe Oloye Balogun ko tọ si ipo naa, nitori pe o ti kọkọ de ade kan gẹgẹ bi ọba.Lekan Balogun wà lára ọba 21 tí Ajimobi fi jẹ, ipò Olubadan kò tọ́ sí i - Amòfin kọ̀wé sí Makinde

Gomina tẹlẹ nipinlẹ Oyo, Oloogbe Abiola Ajimobi lo fi oun ati ogún eeyan mii jẹ gẹgẹ bi ọba nilu Ibadan lasiko iṣakoso Oba Saliu Adetunji to waja lọjọ Aiku.

Àkọlé fídíò, Big Abass gbadura ọdun tuntun fún gbogbo ololufe rẹ

Gẹgẹ bi oun naa ṣe sọ fun BBC, Amofin Orogade sọ pe aini suuru Oloye Balogun nigba naa lo fẹ ẹ da wahala silẹ bayii ninu oye ọba jijẹ nilẹ Ibadan.

O ni ko ṣẹlẹ ri nibi kankan nilẹ Yoruba pe ọba kan gba ade lẹẹmeji.

Àkọlé fídíò, O tó ìdá méjì àwọn ènìyàn àgbáyé to wà nínú ewu àìsàn ibà

Gẹgẹ bi tito oye ilẹ Ibadan, Oloye Ladoja lo tun kan lẹyin Lekan Balogun.

Eyi si lo mu ki amofin Orogade sọ pe Ladoja nikan lo le sọ boya Balogun yoo jẹ Olubadan tuntun tabi ko ni jẹ.

O ni "ti Oloye Ladoja ba fi gbe ẹjọ lọ sile ẹjọ pe oun yoo jọba, ko si ọna abayọ fun Balogun. Idi ni pe o ti gba oye ọba jijẹ rẹ lọwọ Gomina ajimobi, ti ko si tun le jẹ ọba miran mọ.

Àkọlé fídíò, New year prayers: Gbọgbọọgbọ lọwọ́ n yọ ju orí, gbogbo wa laó yọ ju ọ̀tá wa lọ

"Ṣugbọn ti Ladoja ko ba sọ ohunkohun, ti ko si pe ẹjọ tako iyansipo rẹ, ko sewu."

Amofin Orogade ṣalaye pe ọpọlọpọ ọdun sẹyin ni ilana ọba jijẹ nilẹ Ibadan ti wa, ti ko si si iṣoro ri.

Oba Adetunji, Gomina Makinde ati Lekan Balogun

Oríṣun àwòrán, others

Lekan Balogun wà lára ọba 21 tí Ajimobi fi jẹ, ipò Olubadan kò tọ́ sí i - Amòfin kọ̀wé sí Makinde

Agbẹjọ́rò kan kọ lẹ́tà tako gbígbé adé Olubadan lé Lekan Balogun lórí

Agbẹjọro kan to fi ilu Ibadan ṣe ibujoko, Michael Lana ti kọ iwe ẹsun si gomina ipinlẹ Oyo, Seyi Makinde pe ko gbọdọ gbe ade le Oloye Olalekan Balogun lori gẹgẹ bi Olubadan tuntun.

Àkọlé fídíò, Àwọn aláànú ṣe ọdún fáwọn tí kò rí ọwọ́ họrí

Lati ọjọ ti Olubadan tẹlẹ, Oba Saliu Adetunji ti ku ni iroyin ti n lọ kaakiri ori ayelujara pe Lekan Balogun ni oye kan.

Ṣugbọn ninu iwe ẹsun to kọ ni ọjọ Aje, Amofin Lana ṣalaye pe Balogun ati awọn oloye agba miran ti gba ade gẹgẹ bi ọba lasiko isẹjọba gomina tẹlẹ, Oloogbe Abiola Ajimobi.

O ni nitori naa ni gomina Makinde ko gbọdọ fi gbe ade miran le lori gẹgẹ bi Olubadan.

Amofin Lana sọ pe ko si ninu itan ilẹ Yoruba pe ẹni to ti jẹ ọba tun gba igbega bọ si ipo ọba miran.

Tẹ o ba gbagbe, ẹ o ranti pe Gomina Ajimobi fi awọn ọba tuntun mọkanlelogun miran jẹ nilu Ibadan lasiko ti Oba Saliu fi wa lori oye.

Àkọlé fídíò, Prophet Hezekiah New Year Prayer: Gbogbo wa ni ká ṣiṣẹ́ fún ìdàgbàsókè Naijiria

Ọrọ naa fa wahala, debi i pe o di ọrọ ile ẹjọ.

Oloye Lekan Balogun si wa lara awọn ọba mọkanlelogun naa. Koda, lara oun lo fẹ ẹ jẹ olori wọn ninu rogbodiyan ti wọn ba Oba Adetunji fa.

Àkọlé fídíò, Ọdún tó súnmọ́ ìdìbò ni 2022, wọ́n ó ni ta ẹ̀jẹ̀ wa sílẹ̀

Amofin Lana sọ ninu lẹta rẹ pe ko si eyi to tọ si ipo Olubadan ninu awọn ọba mọkanlelogun naa, to fi mọ Lekan Balogun.

O ni oun kọ lẹta naa si Makinde nitori wahala ile ẹjọ to le waye lori iyansipo Lekan Balogun.

Àkọlé fídíò, 'Òṣìṣẹ́ Bánkì ni mí l'Amẹ́ríkà kí n tó bẹ̀rẹ̀ Tíátà'

Lana ni "labẹ awọn ofin ifinijoye, ẹni to ti jẹ ọba ko le gun ori itẹ Olubadan.

"Niwọn igba ti awọn oloye agba naa ṣi n lo oye ọba, wọn o le gun ori itẹ naa. Gbigbe ade Olubadan le ẹnikẹni ninu wọn lori ko si ba ofin mu."

Lẹta

Oríṣun àwòrán, daily post

Lẹta

Oríṣun àwòrán, daily post

Lẹta

Oríṣun àwòrán, daily post