You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Baba Ijesha: Kò sí aṣẹ́wó lára àwọn òṣèré tíátà Yoruba, mi ò sì faramọ́ ìfipábánilòpọ̀ - Olofa Ina
Agbaọjẹ oṣere tiata Yoruba, Deji Aderemi, ti ọpọ mọ si Olofa Ina ti tọrọ aforiji lọwọ awọn oṣere tiata obinrin fun ọrọ to sọ lasiko igbẹjọ Baba Ijesha nile ẹjọ giga ipinlẹ Eko.
O ni ki awọn obinrin naa darijin oun lori ọrọ ti oun sọ pe pupọ ninu wọn ni wọn maa n ba ni ibalopọ lagbo oṣere.
Olofa Ina lo sọ ọrọ naa ninu fidio kan to fi ṣọwọ si awọn akọroyin.
Ṣaaju ni Olofa Ina ti kọkọ sọ pe ko jẹ tuntun pe ibalopọ n waye laarin awọn oṣere tiata ninu ifọrọwerọ kan pẹlu BBC Yoruba lasiko igbẹjọ naa laarin ọsẹ.
Lasiko ti akọroyin BBC bi Olofa Ina leere ohun to gbe wa sile ẹjọ naa, o ni ṣe ni awọn eeyan kan mọọmọ dẹ pakute fun Baba Ijesha lori ẹsun ifipabanilopọ ti wọn fi kan.
Lẹyin naa lo ni oun wa sile ẹjọ lati wa woye ibi ti ẹjọ naa yoo fi si, to si sọ pe ọrọ ibalopọ yii "Ko jẹ itumọ si awa... nitori gbogbo nnkan bayẹn lo n so wa pọ pẹlu awọn obinrin."
- Àwọn agbébọn pa ìyàwò èèkàn olóṣèlú ní Ibadan, ọlọ́pàá ní adigunjalè ní wọ́n
- Kò sí ìgbà tí mo lọ bá àwọn jàǹdùkú nínú igbó tí ìjọba kò mọ̀ si - Sheik Gumi
- Òní ni ìwọ́de Yoruba Nation yóò wáyé ní ìpínlẹ̀ Kwara
- NDLEA mú dókítà àti sọ́jà lórí ẹ̀sùn títà egbòogi olóró
- Ìwé ẹ̀rí àyẹ̀wò oògùn olóró yóò di dandan fún ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ gbé'yàwò láìpẹ́- Buba Marwa NDLEA
- Ẹ wo ọ̀nà àbáyọ tí adigunjalè bá kọ lẹ́tà sí yín pé àwọn fẹ́ ẹ́ wá jà yín lólè
- Ọwọ́ tẹ adigunjalè mẹta nínú ìjàmbá ọkọ̀ ní Ìpínlẹ̀ Ogun
- Wo ìlànà tí ó máa tẹ̀lé láti wo èsì ìdánwò 2021 Jamb UTME rẹ lórí ayélujára àti SMS
O ni "Ko si obinrin to ṣe pataki lode oni ninu iṣẹ tiata ti yoo sọ pe wọn ko ba oun lopọ ri ninu ẹgbẹ" niroti naa ko jẹ tuntun.
Ṣugbọn ọrọ naa ko dun mọ ọpọ awọn eeyan ninu, paapaa awọn obinrin to jẹ oṣere, eyii to mu ki wọn bẹrẹ si n bu ẹnu ẹtẹ lu lori ayelujara.
Wayi o, Olofa Ina ti wa tọrọ aforiji, to si tun sọ pe oun ko ṣegbe lẹyin ki wọn maa fi ipa fi ba obinrin tabi ọmọde lopọ.
O ni ọrọ ti oun sọ jabọ pẹlu itara, ati pe ohun ti oun gbiyanju lati sọ kọ ni awọn eeyan tumọ ọrọ naa si.
O fikun pe "Ẹmabinu ana, paapaa ẹyin obinrin ti ẹ jẹ iya wa nidi iṣẹ tiata."
Agba ọjẹ naa ṣo siwaju si pe kii ṣe aṣa awọn oni tiata ni lati maa fi ọwọ pa obinrin lara lọna aitọ nitori ẹṣẹ ni niwaju Ọlọrun.
O ni ko si aṣẹwo ninu awọn oni tiata, nitori naa ki wọn si fi ori jin oun lori ọrọ ti oun sọ ṣaaju fun awọn akọroyin nile ẹjọ naa.
Lẹyin naa lo ke si awọn to kundun obinrin, ti wọn si n fi ọwọ kan obinrin lọna aitọ lati jawọ ninu irufẹ iwa bẹẹ.
- Kò sí ìgbà tí mo lọ bá àwọn jàǹdùkú nínú igbó tí ìjọba kò mọ̀ si - Sheik Gumi
- Àwọn agbébọn pa ìyàwò èèkàn olóṣèlú ní Ibadan, ọlọ́pàá ní adigunjalè ní wọ́n
- Ọlọ́pàá tó tẹ George Floyed lọ́rùn pa ti rí ẹ̀wọ̀n ọdún méjìlélógún àti oṣù mẹ́fà he l'Amẹrika
- Òní ni ìwọ́de Yoruba Nation yóò wáyé ní ìpínlẹ̀ Kwara
- NDLEA mú dókítà àti sọ́jà lórí ẹ̀sùn títà egbòogi olóró
- Ìwé ẹ̀rí àyẹ̀wò oògùn olóró yóò di dandan fún ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ gbé'yàwò láìpẹ́- Buba Marwa NDLEA
Ki lo ti ṣẹlẹ sẹyin?
Iyabo Ojo, mẹ́nu kúrò lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha ní báyìí tí ọ̀rọ̀ ti dé iwájú mi - Adájọ́ Toyin Taiwo
Adajọ ile ẹjọ ti wọn ti n gbọ ẹjọ lori ẹsun ifipabanilopọ ati iwa ipa ninu ile, Oluwatoyin Taiwo, ti kilọ fun Iyabo Ojo lati mẹnu kuro lori ọrọ Baba Ijesha.
Adajọ náà lo pàṣẹ ọhun lasiko to n gbọ ẹjọ lori ẹsun ifipabanilopọ ti wọn fi kan Baba Ijesha nile ẹjọ náà ni Ikeja, nílùú Eko.
O ni niwọn igba ti ẹjọ náà ti wà níwájú oun, oun ko fẹ kí ẹnikẹni máa sọrọ lórí rẹ mọ lórí ayelujara ki oun le r'oju ráàyè ṣiṣẹ oun gẹgẹ bíi adájọ.
- Ẹ gbà wa o! Ìwé ìrìnà àti ìwé ìgbélùú wa ní Oman ti "expire", wọ́n tún ní Nàìjíríà ti di ibi àìwọ̀
- Ọ̀rọ̀ wo ni Sheikh Gumi sọ tí iléeṣẹ́ ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ DSS ní kó wá ṣàlàyé ara rẹ̀?
- Mó ṣèlérí láti buwọ́lu àtúntò Naijiria, Ilé Aṣòfin o kù sí ọwọ́ yín - Ààrẹ́ Buhari
- Ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà ń ṣelédè lẹ́yìn Ajimobi, èrò wọn ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀!
- Èèyàn kan ti kú, 99 di àwátì lẹ́yìn tí ilé alájà méjìlá wó lulẹ̀ l'óru
- Ọmọ ọdún méje ni mo ti ń digunjalè, ogun ìdílé ló fàá, afurasí ṣàlàyé l'Ondo
- Iná sọọ! Àwọn ọmọdé tó ń kọ́ ìjà ààbò ara ẹni "Kongfu jó ráúráú
Ọrọ naa jẹyọ lasiko ti agbẹjọro Princess Damilola, to fi ẹsun kan Baba Ijesha n fesi sí beeli ti adajọ náà fún Baba Ijesha ṣaaju.
Agbẹjọro Princess sọ pe ọpọ àwọn èèyàn lò ti bẹrẹ sí n dukoko mọ onibara oun lori ẹjọ náà, ati pe o ṣeéṣe kí ẹmi rẹ ti wa ninu ewu.
Ṣugbọn agbẹjọro Baba Ijesha fesi pe awọn alatilẹyin Princess ti ba orukọ onibara oun jẹ lori ayelujara nígbà ti adajọ kò tíì ṣe ìdájọ lori ọrọ ọhun.
O ni awọn eeyan bíi Princess fúnra rẹ àti Iyabo Ojo n gbe ìgbésẹ láti dá ojú ẹjọ náà rú bi wọn ṣe n sọ oríṣiríṣi ọrọ kobakungbe nipa Baba Ijesha loju opo Instagram wọn.
Eyii lo mú kí adajọ Oluwatoyin Taiwo pàṣẹ pé kí gbogbo àwọn tí wọn n fi ẹnu wọn wà rọọfu lori igbẹjọ náà lọ gbẹnu dakẹ, to fi mọ Princess, Iyabo Ojo, Yomi Fabiyi atawọn oṣere tiata Yorùbá mìíràn.
- Wo iléẹ̀kọ́ tí wọ́n kò ti fààyè gba akẹ́kọ̀ọ́ láti padà sọ́dọ̀ Òbí tàbí ìlú rẹ̀ lẹ́yìn tó bá parí
- Ilé ẹjọ́ gba béèlì Baba Ijesha N2Miliọ̀nù ní wọ́n fún
- Hàà! Akẹ́kọ̀ọ́ UNILAG ẹni ọdún 21 kà bòrò-bòrò pé: Èmi ló pa olówó, ọ̀gá Super TV, Usifo Ataga
- Ṣé lóòtọ́ ni Kọmísọ̀nà Fidelis Nweze jíǹde padà? Ohun tí ìjọba sọ rèé
- Ẹyìn tẹ ń gba ojú VPN wọ Twitter, ẹ kò ṣé mí, ará yín lẹ̀ ń ṣé - Lai Mohammed
O ni "Mi o fẹ ki ẹnikẹni máa sọrọ lórí ẹjọ yìí mọ lori ayelujara."
"Ọrọ yòówù tí àwọn èèyàn ba n sọ lori ayelujara ko kan mi, ko si ni ṣàpèjúwe irufẹ ẹjọ ti n o da."
Adajọ Oluwatoyin Taiwo pari ọrọ rẹ pe awọn ẹri to wa níwájú oun ni yóò sọ ibi ti ọrọ naa yóò já sí, kii ṣe ọrọ ti awọn eeyan kan n sọ nigboro, ṣugbọn oun ko fẹ kí wọn sọrọ lórí ẹjọ náà mọ.
Wayi o, adajọ Oluwatoyin Taiwo ti fún Baba Ijesha ni beeli pẹlu mílíọ̀nù méjì naira ati oniduuro meji.
O sí ti sun igbẹjọ ọhun sí ọjọ kẹrindinlọgbọn, ọjọ kẹtadinlogbon ati ọjọ kejidinlọgbọn ọdun yìí.
Ilé ẹjọ́ gba béèlì Baba Ijesha N2Miliọ̀nù ní wọ́n fún
Adajọ ti kede pe miliọnu meji Naira ni ki Baba Ijesha san gẹgẹ bi owo beeli.
Akọroyin BBC to n jabọ lati ile ẹjọ giga to wa ni Ikeja sọ pe awọn agbẹjọro ogun lo wa ṣoju Baba Ijesha lori ẹsun ti wọn fi kan an.
Ṣaaju ni agbẹjọro rẹ ati ti ijọba ti ṣe atotonu wọn tan niwaju adajọ lori idi ti awọn fi f tabi tako ki ileẹjọ gba oniduro rẹ.
- Sàárè òkú 750 dédé wú jádé níléèwè agbo-ilé kan, ìlú dàrú!
- Hàà! Akẹ́kọ̀ọ́ UNILAG ẹni ọdún 21 kà bòrò-bòrò pé: Èmi ló pa olówó, ọ̀gá Super TV, Usifo Ataga
- Alàgbà Gumi, ẹ lọ mèṣọ́nu lórí àwọn ọ̀rọ̀ tó lè máa ki àwọn agbébọn láyà- Iléeṣẹ́ Ológun Nàìjíríà
- Ẹyìn tẹ ń gba ojú VPN wọ Twitter, ẹ kò ṣé mí, ará yín lẹ̀ ń ṣé - Lai Mohammed
- Ẹ̀bùn owó, oúnjẹ, aṣọ àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ ní ìkókó mú wọlè fún ẹbí Kemisola Ogunniyi ní Ondo
- Ajimobi ṣì ń dá wa lọ́rùn, kódà lẹ́yìn ikú! Ìdí rèé tí ẹ ò lè yínmú sí - Oyo APC
Adajọ Oluwatoyin Taiwo si ti gbọ lati ẹnu wọn to wa si ni oun gbe iye owo yi kalẹ pẹlu pe o ni lati mu oniduro meji wa ti ọkan ninu wọn gbọdọ maa gbe nilu Eko.
Agbẹjọro agba SAN, Babatunde Ogala pẹlu Dada Awosika SAN ati awọn agbẹjọro mi ti apapọ wọn jẹ ogun lo wa duro fun Baba Ijesha.
Ninu ọrọ rẹ Baba Ijesha sọ fun adajọ pe oun ko jẹbi ẹsun onigun mẹfa ti wọn fi kan an.
Ni bayi, agbẹjọro ijọba sọ pe awn kan n dunkoko mọ Princess amọ agbẹjọro baba Ijẹsha fesi pada pe Iyabo Ojo ati awọn miran ti ba orukọ Baba Ijesha jẹ lori ayelujara.
Adajọ ti sun igbẹjọ di ọjọ Kẹrindinlọgbọn, Mẹtadinlọgbọn ati Mejidinlọgbọn Oṣu Keje.
Ninu awọn to kọwọrin wa wo bi ẹjọ naa ṣe n lọ lati ri Yomi Fabiyi, Princess ati Baba Olofaina ti gbogbo wọn si jẹ oṣere tiata.
Iyabo Ojo, eléyìí tẹ ṣe lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha tó, tó bá ṣẹ̀yín kí ẹ dáríjì - Ọlọfaina bú sẹ́kún
Gbajugbaja Oṣere ni Naijiria, Deji Aderemi ti ọpọ eniyan mọ si Ọlọfaina ti bẹ Iyabo Ojo ati awọn miran ti ọrọ kan pe ki wọn dariji Baba Ijesha lori ọrọ ifipabanilopọ ti wọn fi kan an.
Olofaina sọ bẹẹ lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ ni ileẹjọ ti igbẹjọ Baba Ijesha tio waye ni Ọjọbọ.
O ni iru eyi ko ṣẹlẹ ri ni agbo oṣere ki wọn ma a gbe ara wọn lọ si ileẹjọ.
- Kí ló mú Olorì Badrat Ajoke kúrò ní ààfin Oyo lọ́jọ́ Iléyá?
- Ẹ̀yin ọmọ Yoruba, ẹ múra láti dìbò ''referendum'' kúrò ní Naijiria, ìjọ̀ba àpapọ̀ à ń bò- Banji Akintoye
- Mo nírètí pé Baba Ijẹsha yóò gba béèlì ní iléẹjọ́ tí yóò tí farahàn lónì - Yomi Fabiyi
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo àti àwọn ẹlẹ́sìn àbáláyé bẹ̀rẹ̀ àjọṣepọ̀ láti fí opin sí ìṣoro ètò aàbò
Gbajugbaja oṣere naa fikun wi pe igbiyanju oun lati ba Iyabo Ojo sọrọ lori iṣẹlẹ naa lo jasi pabo, to si sọ fun oun pe ki oun bọ silẹ nibẹ gẹgẹ bi esi to fun oun, ko to di wi pe o pa foonu mọ oun lẹnu.
Bakan naa ni lo fikun pe oun wa lati ilu Ede,nipinlẹ Osun wa si ileẹjọ lati le wo bi ọrọ naa ma jasi.
Ati wi pe ẹgbẹ ti ṣetan lati ba awọn ti ọrọ naa kan wi, amọ ki wọn parapọ jẹ ọkan.
Mo nírètí pé Baba Ijẹsha yóò gba béèlì ní iléẹjọ́ tí yóò tí farahàn lónì - Yomi Fabiyi
Gbajugbaja oṣere tiata to n ja fun Baba Ijesha, Yomi Fabiyi ti ni oun ni ireti pe Olanrewaju Omiyinka, ti ọpọ eeyan mọ si Baba Ijesha yoo ri beeli rẹ gba loni ni ileẹjọ.
Yomi Fabiyi sọ eyi lasiko to n ba ileeṣẹ iroyin Bbc Yoruba sọrọ lori afojusun rẹ nigba igbẹjọ ti yoo waye ni ileẹjọ to wa ni Ikeja, nipinlẹ Eko.
O ni oun gbagbọ wi pe ko ni si ojusaaju lasiko igbẹjọ naa loni, ti Baba Ijẹsha yoo si gba beeli to tọ si.
''A mọ ilu Eko fun ile ọgbọn, ilu ti wọn fẹran lati ma a fun eniyan ni ẹtọ wọn, ti wọn ki n sii fi ẹt eniyan dun wọn.''
''Beeli to jẹ ti Baba Ijẹsha, mo ni ireti pe yoo ri gba lagbara Ọlọrun''.
Bakan naa ni Yomi Fabiyi fikun pe oun gbagbọ wi pe awọn to lo ọmọbinrin ti ọrọ kan laitọ yoo gba idajọ ti wọn naa loni.
''Awọn ti wọn lo ọmọde naa gbọdọ kọ ẹkọ ki iru rẹ maṣe ṣẹlẹ mọ si awọn ọmọ wa mọ lorilẹede Naijiria''
Yomi Fabiyi ni gbagbaagba ni oun wa lẹyin Baba Ijẹsha, ti oun yoo si wa ni ileẹjọ pẹlu rẹ loni.
Baba Ijesha yóò tún farahàn nílé ẹjọ́ mìí lónìí lórí ẹ̀sùn fífi ipá bá ọmọdé lòpọ̀
Loni Ọjọbọ, ọjọ kẹrinlelogun, oṣu Kẹfa, ọdun 2021, ni wọn o tun gbe oṣerekunrin, Olanrewaju Omiyinka, ti ọpọ eeyan mọ si Baba Ijesha, lọ si ile ẹjọ.
Ẹsun fifi ipa ba ọmọdebinrin ni ibalopọ aitọ ni wọn fi kan Baba Ijesha, eyi ti yoo mu ko farahan niwaju ile ẹjọ to ngbọ awọn akanṣe ẹsun ni Ikeja.
Gbajugbaja apanilẹrin, Princess Comedian si lo gbe lọ si agọ ọlọpaa lẹyin to fi ẹsun kan an pe o ba ikan lara awọn ọmọ to n gbe pẹlu oun lopọ.
- Bí àwọn gbajúmọ̀ ṣe pín rèé lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha
- Princess jèbùrẹ́, ọ̀rọ̀ Baba Ijesha gbóná ju èrò ọ̀pọ̀ èèyàn lọ - Adewale Eleso
- Ẹ̀sùn gbígbìyànjú láti wọ́lé sí ojú ara ọmọdé pẹ̀lú ìpá àtàwọn ẹ̀sùn mìí tí Baba Ijesha yóò jẹ́ rèé
- Ṣé lóòtọ́ ni olè kan wọlè fipá bá ìyá 80 lòpọ̀ nípìnlẹ̀ Ondo?
- Yinka Alaṣeyori fi ọ̀rọ̀ ìjínlẹ̀ púpọ̀ àti omijé ṣàlàyé Oniduro Mi
- Alága ìjọba ìbílẹ̀ Eti-Osa, Eko tí jádé láyé lẹ́yìn tó ṣe àìsàn
- Buhari ní kí ilé aṣòfin àgbà buwọ́lu N895b gẹ́gẹ́ bíi àfikún owó ètò ìṣúná ọdún 2021
Lati ọjọ kejilelogun, oṣu Kẹrin, ni Baba Ijesha ti wa ni ahamọ ọlọpaa.
Ọjọ kẹrindinlogun, oṣu Kẹfa ni wọn kọkọ gbe e lọ sile ẹjọ Majisireeti to wa ni adugbo Yaba.
Awọn ẹsun ti wọn si ka si lẹsẹ ni pe o ṣe ọmọde bi ko ṣe tọ, o ba ọmọde ni ibalopọ, o ki nkan ọmọkunrin rẹ si oju ara ọmọdebinrin, ati ifipabanilopọ.